1Ní àkótán ará, ẹ máa yọ̀ nínú Olúwa wa. Kì í ṣe ìnira fún mi láti kọ̀wé ohun kan náà sí yín, ṣùgbọ́n fún yín ó jẹ́ àìléwu.
2Ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn ajá, ẹ kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn oníṣẹ́-búburú, ẹ sì kíyèsára lọ́dọ̀ àwọn onílà.
3
4
5Ẹnii tí a kọ nílà ní ijọ́ kẹjọ, láti inú kùkùté Ísírẹ́lì wá, láti inú ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì, Hébérù láti inú Hébérù wá; nítorí, ní ti òfin Farisí ni èmi;
6Ní ti ìtara, èmi ń ṣe inúnibínu sí ìjọ; ní ti òdodo tí ó wà nínú òfin, mo jẹ́ aláìlẹ́gàn.
7Ṣùgbọ́n ohunkóhun tí ó ti jásí èrè fún mi, àwọn ni mo ti kà sí òfo nítorí Kírísítì.
8Nítòótọ́ láìṣe àní-àní mo sì ka ohun gbogbo sí òfo nítorí ìtayọ ìmọ̀ Kírísítì Jésù Olúwa mi; nítorí ẹni ti mo ti ṣòfò ohun gbogbo, mo si kà wọn sí ohun tí kò ní láárí, kí èmi lè jèrè Kírísítì,
9Kí a sì lè bá mi nínú rẹ̀, láìní òdodo tí èmi tìkarami, tí ó ti inú òfin wá, ṣùgbọ́n èyí tí ó ti inú ìgbàgbọ́ wá nínú Kírísítì, òdodo láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run nípasẹ̀ ìgbàgbọ́;
10Kí èmi lè mọ̀ ọ́n, àti agbára àjíǹde rẹ̀, àti láti jẹ́ alábàápín nínú ìyà rẹ̀ nígbà tí mo bá faramọ́ ọn nínú ikú rẹ̀;
11Bí ó lè ṣe é ṣe kí èmi lè ní àjíǹde kúrò nínú òkú.
12Kì í ṣe pé ọwọ́ mi ti tẹ̀ ẹ́ ná, tàbí mo ti di pípé: ṣùgbọ́n èmi ń lépa ǹṣó, bí ọwọ́ mi yóò lè tẹ èrè náà nítorí èyí tí a ti dì mí mú pẹ̀lú, láti ọ̀dọ̀ Kírísítì Jésù wá.
13Ará, èmi kò kara mi sí ẹni ti ọwọ́ rẹ̀ ti tẹ̀ ẹ́ ná: Ṣùgbọ́n ohun kan yìí ni èmi ń ṣe, èmi ń gbàgbé àwọn nǹkan tí ó ti kọjá. Lẹ́yìn náà mo ń nàgà wo àwọn nǹkan tí ó wà níwáju.
14Èmi ń lépa láti dé òpin aré-ìje náà fún èrè ìpè gíga Ọlọ́run nínú Kírísítì Jésù.
15Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí àwa tí a dàgbà nípa ti ẹ̀mí ni èrò yìí; bí ẹ̀yin bá sì ní èrò mìíràn nínú ohunkóhun, èyí náà pẹ̀lú ni Ọlọ́run yóò fi hàn yín.
16Kìkì pé, ibi tí a ti dé ná, ẹ jẹ́ kí a máa rìn ní ojú-ọ̀nà kan náà, kí a ni èrò kan náà.
17
18Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ní ń rìn, nípasẹ̀ àwọn ẹni tí mo ti ń wí fún yín nígbàkúùgbà, àní, tí mo sì ń sọkún bí mo ti ń wí fún yín nísinsinyìí, pé, ọ̀ta àgbélébùú Kírísítì ni wọ́n:
19Ìgbẹ̀yìn wọn ni ìparun, ikùn wọn sì ni Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń ṣògo nínú ìtìjú wọn, àwọn ẹni tí ń tọ́jú ohun ti ayé.
20Nítorí ìlú-ìbílẹ̀ wá ń bẹ̀ lọ́run: láti ibi ti àwa pẹ̀lú gbé ń fojúsọ́nà fún Olùgbàlà, Jésù Kírísítì Olúwa.
21