Ìwé Òwe 12:1-28 BYB2014 - Bible AI

1Ẹnikẹ́ni tí ó fẹ́ ẹ̀kọ́ fẹ́ ìmọ̀, ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kórìíra ìbáwí jẹ́ aláìgbọ́n.

2Ènìyàn rere gba ojú rere lọ́dọ̀ OLÚWA ṣùgbọ́n OLÚWA kórìíra alárekérekè ènìyàn.

2

3A kò lè fi ẹsẹ̀ ènìyàn múlẹ̀ nípa ìwà búburú ṣùgbọ́n a kò le è fa Olódodo tu.

3

4Aya oníwà rere ni adé ọkọ rẹ̀ ṣùgbọ́n aya adójútini dàbí ìgbà tí inú egungun rẹ̀ jẹrà.

4

5Ète àwọn Olódodo dára ṣùgbọ́n ìmúra ènìyàn búburú jẹ́ ẹ̀tàn.

5

6Ọ̀rọ̀ ènìyàn búburú lúgọ de ẹ̀jẹ̀ ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ àwọn Olódodo gbà wọ́n là.

6

7A sí àwọn ènìyàn búburú ní ìdí, wọn kò sì sí mọ́; ṣùgbọ́n ilé Olódodo dúró ṣinṣin.

7

8A ń yín ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n ọgbọ́n rẹ̀ ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ọlọ́pọlọ wúruwùru ni a kẹ́gàn.

8

9Ó sàn kí a má jẹ́ ènìyàn pàtàkì kí a sì ní ìránṣẹ́ ju kí a díbọ́n pé a jẹ́ ẹni pàtàkì láì lóúnjẹ.

9

10Ènìyàn rere ń ṣaájò ohun tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ nílò Àmọ́ ìwà tó dára jù tí ènìyàn búburú lè hù, ibi ni.

10

11Ẹni tí ó bá dáko yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ, ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa òjìji lásánlàsàn kò gbọ́n.

11

12Ènìyàn búburú ń fẹ́ ìkógún àwọn ènìyàn ìkà ṣùgbọ́n gbòǹgbò Olódodo ń gbilẹ̀.

12

13A mú ènìyàn búburú nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹsẹ̀ rẹ̀ ṣùgbọ́n Olódodo bọ́ kúrò lọ́wọ́ ìdàámú.

13

14Láti inú èso rẹ̀, ènìyàn kún fún onírúurú ohun rere bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ti ń pín in lérè dájúdájú.

14

15Ọ̀nà aláìgbọ́n dára lójú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n Ọlọgbọ́n ènìyàn a máa gba ìmọ̀ràn.

15

16Aláìgbọ́n ènìyàn fi ìbínú un rẹ̀ hàn lẹ́ṣẹ̀kẹṣẹ̀, ṣùgbọ́n olóye ènìyàn fojú fo ìyànjẹ.

16

17Ẹni tí ó jẹ́ ajẹ́rìí tòótọ́ jẹ́rìí ohun tí ojú rẹ̀ rí ṣùgbọ́n ajẹ́rìí èké máa ń parọ́.

17

18Ọ̀rọ̀ tí a kò rò jinlẹ̀ máa ń gún ni bí ọ̀kọ̀ ṣùgbọ́n ahọ́n ọlọgbọ́n ń mú ìwòsàn wá.

18

19Ètè tí ń sòótọ́ yóò wà láéláé ṣùgbọ́n ahọ́n tí ń parọ́ kì í tọ́jọ́.

19

20Ẹ̀tàn wà nínú ọkàn àwọn tí ń pète búburú ṣùgbọ̀n ayọ̀ wà fún àwọn tí ń mú kí àlàáfíà gbilẹ̀.

20

21Ibi kì í ṣubú lu Olódodo rárá ṣùgbọ́n ènìyàn búburú gba ìpín ìyọnu tiwọn.

21

22OLÚWA kóìríra ètè tí ń parọ́ ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn Olóòótọ́.

22

23Ènìyàn Olóye fi ìmọ̀ rẹ̀ pamọ́ sínú ara rẹ̀ ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú ń gbé ìwà òmùgọ̀ jáde.

23

24Ọwọ́ àìṣọ̀lẹ yóò jọba ṣùgbọ́n ọ̀lẹ ṣíṣe a máa yọrí sí sínsìnrú.

24

25Ìbànújẹ́ ní ọkàn ènìyàn ní dorí rẹ̀ kodò ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ rere a máa mú kó yọ̀.

25

26Olódodo ènìyàn máa ń ṣọ́ra láti dọ́rẹ̀ẹ́ ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ń mú wọn sìnà.

26

27Ọ̀lẹ ènìyàn kò sun ẹran tí ó pa lóko ọdẹ ṣùgbọ́n ẹni tí kì í ṣe ọ̀lẹ máa ń díwọ̀n ohun ìní rẹ̀.

27

28Ní ọ̀nà àwọn Olódodo ni ìyè wà ní ọ̀nà náà ni àìkú wà.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide