1Ọlọ́gbọ́n obìnrin kọ́ ilé e rẹ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n obìnrin fi ọwọ́ ara rẹ̀ wó o.
2Ẹni tí ń rìn déédé bẹ̀rù OLÚWA, ṣùgbọ́n ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ kò tọ́ kẹ́gàn OLÚWA.
2
3Ọ̀rọ̀ aṣiwèrè a máa ṣokùnfà pàsán fún ẹ̀yìn rẹ̀, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ètè ọlọ́gbọ́n a máa dáàbò bò ó.
3
4Níbi tí kò sí ẹran, ibùjẹ ẹran a máa mọ́ tónítóní ṣùgbọ́n, nípa agbára akọ màlúù ni ọ̀pọ̀ ìkórè ti ń wá.
4
5Ẹlẹ́rìí tí ń sòótọ́ kì í tan ni ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí èké a máa tú irọ́ jáde.
5
6Ẹlẹ́gàn ń wá ọgbọ́n kò sì rí rárá, ṣùgbọ́n ìmọ̀ máa ń wà fún olóye.
6
7Má ṣe súnmọ́ aláìgbọ́n ènìyàn, nítorí ìwọ kì yóò rí ìmọ̀ ní ètè rẹ̀.
7
8Ọgbọ́n olóye ni láti ronú jinlẹ̀ nípa ọ̀nà an wọn ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ asìwèrè ni ìtànjẹ.
8
9Aláìgbọ́n ń ṣẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí ó yẹ kí ó ṣe àtúnṣe ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ ṣùgbọ́n láàrin àwọn olódodo ni a ti rí ojú rere.
9
10Ọkàn kọ̀ọ̀kan ló mọ ẹ̀dùn ọkàn tirẹ̀ kò sì sí ẹnìkan tó le è bá ọkàn mìíràn pín ayọ̀ rẹ̀.
10
11A ó pa ilé ènìyàn búburú run Ṣùgbọ́n àgọ́ Olódodo yóò máa gbèrú síi.
11
12Ọ̀nà kan wà tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn, ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín, a máa já sí ikú.
12
13Kódà nígbà tí a ń rẹ́rìnín, ọkàn leè máa kérora; ayọ̀ sì leè yọrí sí ìbànújẹ́.
13
14A ó san án lẹ́kùnrẹ́rẹ́ fún aláìgbàgbọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ Ènìyàn rere yóò sì gba èrè fún tirẹ̀.
14
15Òpè ènìyàn gba ohun gbogbo gbọ́ ṣùgbọ́n Olóye ènìyàn ronú lórí àwọn ìgbéṣẹ̀ rẹ̀.
15
16Ọlọgbọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run ó sì kórìíra ibi ṣùgbọ́n aláìgbọ́n jẹ́ alágídí àti aláìṣọ́ra.
16
17Ẹni tí ó máa ń tètè bínú máa ń hùwà aṣiwèrè, a sì kórìíra eléte ènìyàn:
17
18Òpè jogún ìwà òmùgọ̀ ṣùgbọ́n a dé ọlọgbọ́n ní adé ìmọ̀.
18
19Ènìyàn ìkà yóò tẹríba níwájú àwọn ènìyàn rere àti ènìyàn búburú níbi ìlẹ̀kùn àwọn olódodo.
19
20Kódà àwọn aládùúgbò o talákà kò fẹ́ràn rẹ̀ ṣùgbọ́n, Ọlọ́rọ̀ ní ọ̀rẹ́ púpọ̀.
20
21Ẹni tí ó kẹ́gàn aládùúgbò o rẹ̀ ti dẹ́ṣẹ̀ ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ẹni tí ó ṣàánú àwọn aláìní.
21
22Ǹjẹ́ àwọn tí ń pète ibi kì í sìnà? Ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbérò ohun rere ń rí ìfẹ́ àti òtítọ́.
22
23Gbogbo iṣẹ́ àṣekára ló máa ń mú èrè wá ṣùgbọ́n ẹjọ́ rírò lásán máa ń ta ni lósì ni.
23
24Ọrọ̀ Ọlọgbọ́n ènìyàn ni adé orí wọn ṣùgbọ́n ìwà aláìgbọ́n ń mú ìwà òmùgọ̀ wá.
24
25Ẹlẹ́rìí tí ó ṣòótọ́ gba ẹ̀mí là ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí èké jẹ́ ẹlẹ́tàn.
25
26Ẹni tí ó bẹ̀rù OLÚWA ni ilé ìṣọ́ ààbò yóò sì tún jẹ́ ààbò fún àwọn ọmọ rẹ̀.
26
27Ìbẹ̀rù OLÚWA jẹ́ oríṣun ìyè, tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìkẹ́kùn ikú.
27
28Ènìyàn púpọ̀ ní ìlú jẹ́ ògo Ọba, ṣùgbọ́n láì sí ìjòyè, Ọba á parun.
28
29Onísùúrù ènìyàn ní òye tí ó pọ̀, ṣùgbọ́n onínú fùfù ènìyàn máa ń fi ìwà aṣiwèrè hàn.
29
30Ọkàn tí ó lálàáfíà fi ìyè mú kí ọjọ́ ayé gùn fún ara, ṣùgbọ́n ìlara mú kí egungun jẹrà.
30
31Ẹni tí ó fi ìyà jẹ aláìní ń fi ìkórìíra hàn ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó ṣoore fún aláìní bu ọlá fún Ọlọ́run.
31
32Nígbà tí ìyọnu bá dé, a fa àwọn búburú lulẹ̀, kódà nínú ikú àwọn olódodo ni ààbò.
32
33Ọgbọ́n wà nínú ọkàn olóye kódà láàrin àwọn aláìlóye, ó jẹ́ kí wọn mọ òun.
34Ododo a máa gbé orílẹ̀ èdè ga, ṣùgbọ́n ìtìjú ni ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ fún àwùjọ káwùjọ.
34
35Ọba a máa ní inú dídùn sí ìránṣẹ́ tí ó gbọ́n ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ wá sórí ìránṣẹ́ adójútini.