1Ìdáhùn pẹ̀lẹ́ yí ìbínú padà ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ líle máa ń ru ìbínú sókè.
2Ahọ́n ọlọgbọ́n a máa gbé ìmọ̀ jáde ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń tú ọ̀rọ̀ ọ òmùgọ̀ jáde.
2
3Ojú OLÚWA wà níbi gbogbo, Ó ń wo àwọn ẹni búburú àti àwọn ẹni rere.
3
4Ahọ́n tí ń mú ìtura wá jẹ́ igi ìyè ṣùgbọ́n ahọ́n ẹ̀tàn ń pa ẹ̀mí run.
4
5Aláìgbọ́n ọmọ kọ ìbáwí baba rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí jẹ́ ọlọgbọ́n.
5
6Ilé olódodo kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìṣúra, ṣùgbọ́n èrè àwọn ènìyàn búburú ń mú ìyọnu wá fún wọn.
6
7Ètè olódodo ń tan ìmọ̀ kalẹ̀; ṣùgbọ́n kò rí bẹ́ẹ̀ fún ọkàn aláìgbọ́n.
7
8OLÚWA kórìíra ìrúbọ àwọn ènìyàn búburú ṣùgbọ́n àdúrà olódodo tẹ́ẹ lọ́rùn.
8
9OLÚWA kórìíra ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ṣùgbọ́n ó fẹ́ràn àwọn tí ń lépa òdodo.
9
10Ẹni tí ó kúrò lójú ọ̀nà yóò rí ìbáwí gan an, ẹni tí ó kórìíra ìbáwí yóò kú.
10
11Ikú àti ìparun sí sílẹ̀ níwájú OLÚWA mélòó mélòó ní nínú ọkàn àwọn ènìyàn.
11
12Ẹlẹ́gàn kórìíra ìbáwí: kò ní gbàmọ̀ràn lọ́dọ̀ ọlọ́gbọ́n.
12
13Inú dídùn máa ń mú kí ojú túká ṣùgbọ́n ìbànújẹ́ ọkàn máa ń pa ẹ̀mí run.
13
14Ọkàn olóye ń wá ìmọ̀ ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń fẹ́ ìwà òmùgọ̀ bí ẹní jẹun.
14
15Gbogbo ọjọ́ àwọn olùpọ́njú jẹ́ ibi, ṣùgbọ́n ọkàn tí ń dunnú a máa Jàṣè ṣáá.
15
16Ó sàn kí ó má pọ̀, kí ìbẹ̀rù OLÚWA sì wà ju ọrọ̀ púpọ̀ pẹ̀lú ìyọnu.
16
17Oúnjẹ ewébẹ̀ níbi tí ìfẹ́ wà sàn ju àbọ́pa màlúù tòun ti ìríra.
17
18Ènìyàn onínú ríru dá ìjà sílẹ̀ ṣùgbọ́n onísùúrù paná ìjà.
18
19Ẹ̀gún dí ọ̀nà ọ̀lẹ ṣùgbọ́n pópónà tí ń dán ni ti àwọn dídúró ṣinṣin.
19
20Ọlọgbọ́n ọmọ mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ọmọ kẹ́gàn baba rẹ̀.
20
21Inú ènìyàn aláìlóye a máa dùn sí ìwà òmùgọ̀; ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa rin ọ̀nà tààrà.
21
22Ìgbèrò a máa dasán níbi tí kò sí ìmọ̀ràn; ṣùgbọ́n a máa yege níbi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràwà.
22
23Inú ènìyàn a máa dùn nígbà tí ó bá fèsì tó báa mu ọ̀rọ̀ tí ó bá sì wá lásìkò tó yẹ dára púpọ̀!
23
24Ọ̀nà ìyè ń lọ sókè fún ọlọgbọ́n láti sọ kí ó má bá à sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú.
24
25OLÚWA fa ilé onígbéraga ya lulẹ̀, Ṣùgbọ́n ó pa ààlà opó mọ́ láìyẹ̀.
25
26OLÚWA kórìíra èrò ènìyàn búburú,
26
27Ọ̀kánjúwà ènìyàn mú ìyọnu bá ilé rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóò yè.
27
28Ọkàn olódodo ń wọn ìdáhùn wò ṣùgbọ́n ẹnu ènìyàn búburú ń tú ibi jáde.
28
29OLÚWA jìnnà sí ènìyàn búburú ṣùgbọ́n ó ń gbọ́ àdúrà olódodo.
29
30Ojú tó túká máa ń mú ayọ̀ wá fún ọkàn, ìròyìn ayọ̀ sì ń mú ìlera wá sínú egungun.
30
31Ẹni tí ó fetí sí ìbáwí tí ń fún ni ní ìyè, yóò wà ní àpéjọpọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n.
31
32Ẹni tí ó kọ̀ ìbáwí kẹ́gàn ara rẹ̀, Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí yóò ní ìmọ̀ síi.
32
33Ìbẹ̀rù OLÚWA kọ́ ènìyàn ní ọgbọ́n, Ìrẹ̀lẹ̀ sì ni ó máa ń ṣáájú ọlá.