Ìwé Òwe 16:1-33 BYB2014 - Bible AI

1Ti ènìyàn ni ìgbèrò inú ọkàn Ṣùgbọ́n láti ọ̀dọ̀ OLÚWA ni ìdáhùn ahọ́n ti ń wá.

2Gbogbo ọ̀nà ènìyàn ni ó dà bí i pé ó dára lójú ara rẹ̀ Ṣùgbọ́n OLÚWA ló ń díwọ̀n èrò inú ọkàn.

2

3Fi ohun gbogbo tí o bá ṣe lé OLÚWA lọ́wọ́ Èrò rẹ yóò sì ṣe é ṣe.

3

4OLÚWA ti ṣe ohun gbogbo láti mú kí ó rí bí ó ṣe fẹ́ Kódà ènìyàn búburú fún ọjọ́ ìpọ́njú.

4

5OLÚWA kórìíra gbogbo ẹni tí ń gbéraga lọ́kàn rẹ̀ mọ èyí dájú pé wọn kò ní lọ láìjìyà.

5

6Nípaṣẹ̀ ìfẹ́ àti òtítọ́ a ṣètùtù ẹ̀ṣẹ̀ nípaṣẹ̀ ìbẹ̀rù OLÚWA ènìyàn sá fún ibi.

6

7Nígbà tí ọ̀nà ènìyàn bá tẹ́ OLÚWA lọ́rùn, yóò mú kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ gàn-án bá a gbé ní àlàáfíà.

7

8Ó sàn kí ó kéré pẹ̀lú òdodo ju èrè púpọ̀ pẹ̀lú èrú.

8

9Ènìyàn a máa pète ọ̀nà ara rẹ̀ lọ́kàn an rẹ̀ ṣùgbọ́n OLÚWA ní í pinnu ìgbésẹ̀ rẹ̀.

9

10Ètè ọba a máa sọ̀rọ̀ nípa inú síi ẹnu rẹ̀ kò gbọdọ̀ gbé ẹ̀bi fún ara rẹ̀.

10

11Òdiwọ̀n àti òṣùwọ̀n òtítọ́ wá láti ọ̀dọ̀ OLÚWA; gbogbo wíwúwo àpò jẹ́ láti ọwọ́ rẹ̀.

11

12Àwọn ọba kórìírà ìwà àìtọ́ nítorí òdodo ní í fi ìdí ìtẹ́ múlẹ̀.

12

13Àwọn ọba ní inú dídùn sí ètè tí ń ṣòótọ́ ènìyàn tí ń sọ òtítọ́ ṣe iyebíye sí wọn.

13

14Ìrànṣẹ́ ikú ni ìbínú ọba jẹ́ ṣùgbọ́n ọlọgbọ́n ènìyàn yóò tù ú nínú.

14

15Nígbà tí ojú ọba bá túká, ó túmọ̀ sí ìyè; ojú rere rẹ̀ dàbí i ṣíṣú òjò ní ìgbà òjò.

15

16Ó ti dára tó láti ní ọgbọ́n ju wúrà lọ àti láti yan òye dípò o fàdákà!

16

17Òpópó ọ̀nà àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yàgò fún ibi, ẹni tí ó ṣọ́ ọ̀nà rẹ̀, ṣọ́ ẹnu ara rẹ̀.

17

18Ìgbéraga ní í ṣáájú ìparun, agídí ọkàn ní í ṣáájú ìṣubú,

19ó sàn láti jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ ọkàn láàrin àwọn olùpọ́njú jù láti máa pín ìpín pẹ̀lú àwọn agbéraga.

19

20Ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé ẹ̀kọ́ yóò rí ire, ìbùkún sì ni fún ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ lé OLÚWA.

20

21Àwọn tí ó gbọ́n nínú ọkàn là ń pè ní olóye ọ̀rọ̀ ìtura sì ń mú ẹ̀kọ́ gbèrú.

21

22Òye jẹ́ oríṣun ìyè fún àwọn tí ó ní i, ṣùgbọ́n ìwà òmùgọ̀ ń kó ìyà jẹ aláìgbọ́n.

22

23Ọkàn ọlọgbọ́n ènìyàn a máa ṣọ́ ẹnu rẹ̀ ètè rẹ̀ sì ń mú kí ẹ̀kọ́ gbèrú.

23

24Ọ̀rọ̀ ìtura dàbí afárá oyin ó dùn fún ọkàn, ó sì fi ìlera fún egungun.

24

25Ọ̀nà kan tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn a ṣokùnfà ikú.

25

26Ìfẹ́-àti-jẹun alágbàṣe ń ṣiṣẹ́ fún un nítorí ebi rẹ̀ mú kí ó máa ṣiṣẹ́ ni.

26

27Ènìyàn búburú ń pète ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì dàbí i iná tí ń jóni.

27

28Aláyìídáyidà ènìyàn dá ìjà sílẹ̀ olófòófó a sì máa pín ọ̀rẹ́ kòríkòsùn níyà.

28

29Oníjàgídíjàgan ènìyàn tan aládùúgbò rẹ̀ ó sì mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà tí kò dára.

29

30Ẹni tí ń ṣẹ́jú ń pètekéte; ẹni tí ó ṣu ẹnu jọ ń pète aburú.

30

31Ewú orí jẹ́ ògo ìgbé ayé òdodo ní í múni débẹ̀.

31

32Ó sàn láti jẹ́ oníṣùúrù ju ajagun ènìyàn lọ, ẹni tí ó pa ìbínú mọ́ra ju ajagun-gbàlú lọ.

32

33A ṣẹ́ kèké dàsí ìṣẹ́po aṣọ, ṣùgbọ́n gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ wá láti ọ̀dọ̀ OLÚWA.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide