Ìwé Òwe 19:1-29 BYB2014 - Bible AI

1Ó sàn kí èèyàn jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ kò lábùkù ju aláìgbọ́n tí ètè rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà.

2Kò dára láti ní ìtara láì ní ìmọ̀ tàbí kí ènìyàn kánjú kí ó sì sìnà.

2

3Ìwà òmùgọ̀ ènìyàn fúnra rẹ̀ a pa ẹ̀mí rẹ̀ run; ṣíbẹ̀ ọkàn rẹ̀ yóò máa bínú sí OLÚWA.

3

4Ọrọ̀ má a ń fa ọ̀rẹ́ púpọ̀; ṣùgbọ̀n ọ̀rẹ́ ẹ talákà tún kọ̀ ọ́ sílẹ̀.

4

5Ajẹ́rìí èké kò ní lọ láì jìyà, ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde kò ní lọ lọ́fẹ̀ẹ́.

5

6Ọ̀pọ̀ ń wá ojú rere Olórí; gbogbo ènìyàn sì ni ọ̀rẹ́ ẹni tí ó lawọ́.

6

7Gbogbo ará ilé e talákà ni ó pa á tì mélòómélòó ni ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí ń sá fún un! Bí ó tilẹ̀ ń lé wọn kiri pẹ̀lú ẹ̀bẹ̀, kò tilẹ̀ rí wọn rárá.

7

8Ẹni tí ó gba ọgbọ́n fẹ́ràn ọkàn ara rẹ̀; ẹni tí ó bá káràmáṣìkí òye yóò gbèrú.

8

9Ajẹ́rìí èké kì yóò lọ láìjìyà ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde yóò parun.

9

10Kò yẹ aláìgbọ́n láti máa gbé nínú ọlá ńlá, mélòó mélòó bí ó ti burú tó fún ẹrú láti jọba lórí ọmọ aládé.

10

11Ọgbọ́n ènìyàn a máa fún un ní ṣùúrù; fún ògo rẹ̀ ni láti fojú fo àṣìṣe dá.

11

12Ìbínú ọba dàbí kíke e kìnnìún, ṣùgbọ́n ojúrere rẹ̀ dàbí ìrì lára koríko.

12

13Aláìgbọ́n ọmọ jẹ́ ìparun baba rẹ̀, Aya tí ó máa ń jà sì dàbí ọ̀sọ̀ọ̀rọ̀ òjò.

13

14A máa ń jogún ilé àti ọrọ̀ lọ́dọ̀ òbí ṣùgbọ́n aya olóye láti ọdọ̀ OLÚWA ni.

14

15Ọ̀lẹ ṣíṣẹ́ máa ń fa oorun sísùn fọnfọnfọn ebi yóò sì máa pa ènìyàn tí ó lọ́ra.

15

16Ẹni-kẹ́ni tí ó gbọ́ ẹ̀kọ́ pa ẹnu rẹ̀ mọ́ ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá kẹ́gàn ọ̀nà rẹ̀ yóò kú.

16

17Ẹni tí ó ṣáànú talákà, OLÚWA ní ó yá yóò sì pín in lérè ohun tí ó ti ṣe.

17

18Bá ọmọ rẹ wí nítorí nínú ìyẹn ni ìrètí wà; àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ lọ́wọ́ nínú iparun un rẹ̀.

18

19Ènìyàn onínú-fùfù gbọdọ̀ gba èrè ìwà rẹ̀ bí ìwọ bá gbàá là, ìwọ yóò tún ní láti ṣe é lẹ́ẹ̀kan síi.

19

20Fetí sí ìmọ̀ràn kí o sì gba ẹ̀kọ́ ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín ìwọ yóò di ọlọ́gbọ́n.

20

21Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ète inú ọkàn ènìyàn ṣùgbọ́n ìfẹ́ OLÚWA ní ó máa ń borí.

21

22Ohun tí ènìyàn ń fẹ́ ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀; ó sàn láti jẹ́ talákà ju òpùrọ́ lọ.

22

23Ìbẹ̀rù OLÚWA ń mú ìyè wá: nígbà náà ọkàn ń balẹ̀, láì sí ewu.

23

24Ọ̀lẹ ki ọwọ́ rẹ̀ bọ inú àwo oúnjẹ; kò tilẹ̀ ní mú u padà wá sí ẹnu rẹ̀.

24

25Na ẹlẹ́gàn, òpè yóò sì kọ́gbọ́n; bá olóye ènìyàn wí, yóò sì ní ìmọ̀ síi.

25

26Ẹni tí ó já baba rẹ̀ lulẹ̀, tí ó sì lé ìyá rẹ̀ jáde ó jẹ́ adójútini ọmọ.

26

27Yéé tẹ́tí sí ẹ̀kọ́ tí í mú ni ṣìnà ọmọ mi, ìwọ kì yóò sì sìnà kúrò nínú ọ̀rọ̀ ìmọ̀.

27

28Ajẹ́rìí tí ó bàjẹ́ máa ń kẹ́gàn ìdájọ́ òtítọ́ ẹnu ènìyàn búburú sì ń gbé ibi mi.

28

29A ti pèṣè ìjìyà sílẹ̀ fún ẹlẹ́gàn; àti pàṣán fún ẹ̀yìn aláìgbọ́n.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide