9
10Ta ni ó le rí aya oníwà rere? Ó níye lórí ju iyùn lọ
11ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lẹ́ púpọ̀ nínú rẹ̀ kò sì sí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.
12Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
13Ó sa aṣọ irun àgùtàn olówùú àti ọ̀gbọ̀ Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.
14Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò; ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jínjìn
15Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn; ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀ àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́-bìnrin rẹ̀.
16Ó kíyèsí oko kan, ó sì rà á; nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin àjàrà rẹ̀
17Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbáratagbára Apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́
18Ó ríi pé òwò òun pé fìtílà rẹ̀ kì í sìí kú ní òru
19Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú
20ó la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn talákà ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.
21Nígbà tí òjò dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀ nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.
22Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀; ẹwu dáradára àti eléṣè é àlùkò ni aṣọ rẹ̀
23A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibòde ìlú níbi tí ó ń jókòó láàrin àwọn àgbà ìlú
24Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò
25Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.
26A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀
27Ó ń bojú tó gbogbo ètò ilé rẹ̀ kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́
28Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un
29“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ òbìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ”
30Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù OLÚWA yẹ kí ó gba oríyìn
31sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibòde ìlú.