Ìwé Jóòbù 25:1-6 BYB2014 - Bible AI

1Ígbà náà ní Bílídádì, ará Ṣúà, dáhùn wí pé:

2“Ìjọba àti ẹ̀ru ḿbẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀, òun ní iṣe ìlàjà ní ibi gígagíga ọ̀run.

3Àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ha ní ìyè bí, tàbí ara tani ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ kò tàn sí?

4Èé ha ti ṣe tí a ó fi dá ènìyàn láre lọ́dọ̀ Ọlọ́run? Tàbí ẹni tí a bí láti inú obìnrin wá yóò ha ṣe mọ́?

5Kíyèsí i, òṣùpá kò sì lè í tàn ìmọ́lẹ̀, àní àwọn ìràwọ kò mọ́lẹ̀ ní ojú rẹ̀.

6Áḿbọ̀torí ènìyàn tí iṣe ìdin, àti ọmọ ènìyàn tí iṣe kòkòrò!”

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
>