1“Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
2Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
3Ènìyàn ni ó parí òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí òkúta òkùnkùn àti ti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
4Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jìn sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹṣẹ̀ ènìyàn gbàgbé; wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
5Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìṣàlẹ̀ ni ó yí sókè bí ẹni pé iná.
6Òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta Sáfírì, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
7Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí;
8Àwọn ẹrankan agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
9Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
10Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
11Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún —kún-ya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
11
12“Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
13Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
14Ọ̀gbun wí pé, kò sí nínú mi; omi òkun sì wí pé, kò si nínú mi.
15A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùnwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
16A kò le è fi wúrà Ófírì, tàbí òkútà Óníkísì iyebíye, tàbí òkúta Sáfírì díye lé e.
17Góòlù àti òkúta Kírísítalì kò tó ẹgbẹ́rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èló wúrà ṣe pàsípààrọ̀ rẹ̀.
18A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta Jásípérì; iye ọgbọ́n sì ju òkúta Rubì lọ.
19Òkùta tópásì ti Kúsì kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
19
20“Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21A rí i pé, ó farasinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22Ibi ìparun (Ábádónì) àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé
24Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25Láti dà òṣùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òṣùwọ̀n wọ̀n omi.
26Nígbà tí ó pàsẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27Nígbà náà ni órí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, ‘Kíyè sí i ẹ̀rù OLÚWA èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.’ ”