Ìwé Jóòbù 34:1-37 BYB2014 - Bible AI

1Nígbà náà ni Élíhù dáhùn, ó sì wí pé:

2“Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.

3Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò, bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.

4Ẹ jẹ́ kí a ṣà ẹ̀tọ́ yàn fún ara wa; ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrin wa.

4

5“Nítorí pé Jóòbù wí pé, ‘Aláìlẹ́sẹ̀ ni èmi; Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.

6Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí, bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi, ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán dídì ọgbẹ́.’

7Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jóòbù, tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?

8Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.

9Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn, tí yóò fí máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’

9

10“Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetí sílẹ̀ sí mi ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye: Ódodi fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú àti fún Olódùmárè, tí yóò fí ṣe àìṣedéédéé!

11Nítorí pé ó ń sá fún ènìyàn fún ohun tí a bá ṣe, yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.

12Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkúwà; bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.

13Ta ni ó yàn ań lórí, tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lée lọ́wọ́?

14Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀ tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,

15gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀, ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.

15

16“Ǹjẹ́ nisinsìnyí, bí ìwọ bá ní òye, gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.

17Ẹni tí ó kóríra òtítọ́ ha le iṣe olórí bí? Ìwọ ó hà sì dá olóótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?

18O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ènìyàn búburú ní ìwọ, tàbí fún àwọn ọmọ aládé pé, ìkà ni ẹ̀yin;

19Ańbọ̀tórí fún ẹni tí kì í ṣójúṣàájú àwọn ọmọ-aládé tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí talákà lọ. Nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?

20Ní ìṣẹ́jú kán ni wọn ó kú, láàrin ọ̀gànjọ́ àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́, wọn a sì kọjá lọ; A sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.

20

21“Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa-ọ̀nà ènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.

22Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí ojìjì ikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.

23Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsí ẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.

24Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmìíràn dípò wọn,

25nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn, ó sì yí wọn po ní òru; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ́rẹ́ pọ̀.

26Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn níbi tí àwọn ẹlòmìíràn rí i,

27nítorí pé wọ́n padà sẹ́yìndà sí i, wọn kò sì fi yè sí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,

28kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní

29ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi? Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i? Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe é orilẹ̀ èdè tàbi sí ènìyàn kan ṣoṣo;

30Kí àgàbàgebè kí ó má báà jọba kí wọn kí ó má di ìdẹ̀wò fún ènìyàn.

30

31“Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé, èmi jẹ̀bí; èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?

32Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi bi mo bá sì dẹ́sẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.

33Íṣe bí ti inú rẹ̀ pe òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà? Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́ tàbí ìwọ ìbá fẹ́ kì í ṣe èmi; Pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ!

33

34“Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi, àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,

35‘Jóòbù ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’

36Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jóòbù wò dé òpin, nítorí ìdahùn rẹ̀ dà bí i ti ènìyàn búburú:

37Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ó pàtẹ́wọ́ ní àárin wa, ó sì sọ ọ̀rọ̀ di púpọ̀ sí Ọlọ́run.”

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
v>