1Nísinsìnyìí nígbà tí Bálámù rí i wí pé ó tẹ́ Ọlọ́run lọ́rùn láti bùkún àwọn Ísírẹ́lì, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá ihà.
2Nígbà tí Bálámù wo ìta ó sì rí Ísírẹ́lì tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
3ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀:
3“Ó wí pé Bálámù ọmọ Béórì,òwe ẹni tí ojú rẹ̀ mọ́lẹ̀,
4Òwe ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè,ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì là:
6“Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde,gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá,gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí OLÚWA gbìn,gẹ́gẹ́ bí igi òpépé tí ó wà lẹ́bá odò.
7Omi yóò sàn láti inú garawa:èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
7“Ọba wọn yóò ga ju Ágágì lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
8“Ọlọ́run mú wọn jáde láti Éjíbítì wá;wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.Wọ́n jẹ orílẹ̀ èdè run,wọ́n fọ́ egungun wọn sí wẹ́wẹ́;wọ́n fi idà wọn gún wọn.
9ⓐ Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún,bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn?
9“Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
10Nígbà náà ni ìbínú Bálákì sì dé sí Bálámù. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀ta mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
11Nísinsìnyìí kúrò lọ́dọ̀ mi kíákíá kí o sì máa relé! Mo sọ wí pé màá sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n OLÚWA kò jẹ́ kí o gba èrè yìí.”
12Bálámù dá Bálákì lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
13‘Kó dà bí Bálákì bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, n kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin OLÚWA: ohun tí OLÚWA bá wí ni èmi ó sọ’?
14Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
15Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Bálámù ọmọ Béórì,òwe ẹnì tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
16òwe ẹni kan tí etí rẹ̀ ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,tí ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ẹni gíga jùlọ,tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè,ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì sí:
16
17“Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí,Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́.Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jákọ́bù;yóò yọ jáde láti Ísírẹ́lì.Yóò tẹ̀ fọ́ orí Móábù,yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Ṣéétì.
18Wọn yóò borí Édómù;yóò ṣẹ́gun Ṣéérì ọ̀ta rẹ̀,ṣùgbọ́n Ísírẹ́lì yóò dàgbà nínú agbára.
19Olórí yóò jáde láti Jákọ́bùyóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
20Nígbà náà ni Bálámù rí Ámálékì ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ámálékì ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀ èdè,ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
21Nígbà náà ní ó rí ará Kénitì ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe:“Ibùgbé rẹ ní ààbò,ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
22ṣíbẹ̀ ẹ̀yin ará Kenítì ni yóò di píparunnígbà tí Áṣúrì bá mú yín ní ìgbékùn.”
23Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Áì, ta ni ó lè yè nigbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
24Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdó kọ̀ Kítímù;wọn yóò ṣẹ́gun Áṣù àti Ébérì,ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
25Nígbà náà ni Bálámù dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Bálákì sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.