Ìwé Nọ́ḿbà 26:1-65 BYB2014 - Bible AI

1ⓐ  Lẹ́yìn àjàkálẹ̀-àrùn OLÚWA sọ fún Mósè àti Élíásárì ọmọ Árónì, àlùfáà pé

2“Ka iye gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọ́n; láti ẹni ogun (20) ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó lè jà lójú ogun ní Ísírẹ́lì.”

3Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ ti Móábù pẹ̀lú Jọ́dánì tí ó kọjá Jẹ́ríkò, Mósè àti Élíásárì àlùfáà sọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn ó wí pé,

4“Ka iye àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ọmọ ogun (20) ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, gẹ́gẹ́ bí OLÚWA ti paláṣẹ fún Mósè.”

4Èyí ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí ó jáde láti Éjíbítì wá:

5ⓑ Àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àkọ́bí ọmọkùnrin Ísírẹ́lì, láti ẹni ti ìdílé Hánókù, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé Hánókù ti jáde wá; Láti ìdílé Pálù, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé àwọn ọmọ Pálù ti jáde wá;

6ti Hésírónì, ìdílé àwọn ọmọ Hésírónì;

6ti Kárímì, ìdílé àwọn ọmọ Kárímì.

7Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Rúbẹ́nì; àwọn tí a sì kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé ẹgbẹ̀sán ó dín àádọ́rin (43,730).

8Àwọn ọmọkùnrin Pálù ni Élíábù,

9àwọn ọmọkùnrin Élíábù ni Némúélì àti Dátanì àti Ábírámù. Èyí ni Dátanì àti Ábírámù náà tí wọ́n ní òkìkí nínú ìjọ tí ó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ sí Mósè àti Árónì tí ó sì wà lára àwọn ẹgbẹ́ Kórà nígbà tí wọ́n bá OLÚWA jà.

10Ilẹ̀ sì la ẹnu rẹ̀, ó sì gbé wọn mì pọ̀ pẹ̀lú Kórà, nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kú níbi tí iná ti run àwọn àádọ́tàlérúgba ọkùnrin (250). Tí wọ́n sì di àmì ìkìlọ̀.

11Àwọn ọmọ Kórà, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.

12Àwọn ọmọ ìrán Símónì bí ìdílé wọn: ti Némúélì, ìdílé Némúélì; ti Jámínì, ìdílé Jámínì; ti Jákínì, ìdílé Jákínì;

13ti Ṣérà, ìdílé Ṣérà;

13tí Ṣọ́ọ̀lù, ìdílé Ṣọ́ọ̀lù.

14Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Símónì, ẹgbàámọ́kànlá ó lé igba. (22,200) ọkùnrin.

15Àwọn ọmọ Gádì bí ìdílé wọn: ti Ṣéfónì, ìdílé Ṣéfónì; ti Hágígì, ìdílé Hágígì; ti Ṣúnì, ìdílé Ṣúnì;

16ti Ósínì, ìdílé Ósíní;

16ti Érì, ìdílé Érì;

17ti Árédì, ìdílé Árédì;

17ti Árólì, ìdílé Árólì.

18Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gádì tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (40,500).

19Àwọn ọmọ Júdà ni Érì àti Ónánì, ṣùgbọ́n Érì àti Ónánì kú ní ilẹ̀ Kénánì.

20Àti àwọn ọmọ Júdà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣélà, ìdílé Ṣélà; ti Pérésì, ìdílé Pérésì; ti Sérà, ìdílé Ṣérà.

21Àwọn ọmọ Pérésì: ti Hámúlù, ìdílé Hámúlù.

21ti Hésírónì, ìdílé Hésírónì;

22Wọ̀nyí ni ìdílé Júdà; gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógójì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. (76,500).

23Àwọn ọmọ Isákárì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Tólà, ìdílé Tólà; ti Púfà, ìdílé Púfà;

24ti Jáṣúbù, ìdílé Jáṣúbù;

24ti Ṣímírónì, ìdílé Ṣímírónì.

25Wọ̀nyí ni ìdílé Isákárì gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàáméjìlélọ́gbọ̀n ó léọ̀ọ́dúnrún (64,300).

26Àwọn ọmọ Ṣebúlúnì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Sẹ́rẹ́dì, ìdílé Ṣẹ́rẹ́dì; ti Élónì, ìdílé Élónì; ti Jálélì, ìdílé Jálélì.

27Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Sebúlúnì gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (60,500).

28Àwọn ọmọ Jósẹ́fù gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; Mánásè àti Éfúráímù:

29Àwọn ọmọ Mánásè: ti Mákírì, ìdílé Mákírì (Mákírì sì bí Gílíádì); ti Gílíádì, ìdílé àwọn ọmọ Gílíádì.

30Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gílíádì: ti Hélékì, ìdílé Hélékì

30ti Íésérì, ìdílé Íésérì;

31àti ti Ásíríẹ́lì, ìdílé Ásíríẹ́lì;

31àti ti Ṣékémù, ìdílé Ṣékémù;

32àti Ṣemídà, ìdílé àwọ ọmọ Ṣemídà;

32àti ti Heférì, ìdílé àwọn ọmọ Héférì.

33(Selofehádì ọmọ Héférì kò sì ni ọmọkùnrin, bí kò ṣe ọmọbìnrin; orúkọ àwọn ọmọbìnrin Selofehádì ni Málà, Nóà, àti Hógílà, Mílíkà àti Táṣà).

34Wọ̀nyí ni ìdílé Mánásè tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàámẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin (52,700).

35Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Éfúráímù gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: láti ọ̀dọ̀ Ṣútẹ́là, ìdílé àwọn ọmọ Ṣútẹ́là; ti Békérì, ìdílé àwọn ọmọ Békérì; ti Táhánì, ìdílé àwọn ọmọ Táhánì.

36Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ṣútélà:

36ti Éránì, ìdílé àwọn ọmo Éránì;

37Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Éfurémù, àwọn tí a kà nínú wọn sì jẹ́ ẹgbàámẹ́rìndínlógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (32,500). Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jóṣẹ́fù gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.

38Àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn nì yí: tí Bẹ́là, ìdílé àwọn ọmọ Bẹ́là; ti Ásíbérì, ìdílé àwọn ọmọ Ásíbérì; ti Áhírámù, ìdílé àwọn ọmọ Áhírámù;

39ti Ṣúfámù, ìdílé àwọn ọmọ Ṣúfámù;

39ti Húfámù, ìdílé àwọn ọmọ Húfámù.

40Àwọn ọmọ Bẹ́là ní pasẹ̀ Árídì àti Náámánì nì yí: ti Náámánì, ìdílé àwọn ọmọ Náámánì.

40ti Árádì, ìdílé àwọn ọmọ Árádì;

41Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì; gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; àti àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàáméjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀jọ (45,600).

42Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dánì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣúhámù, ìdílé àwọn ọmọ Ṣúhámù Wọ̀nyí ni ìdílé Dánì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:

43Gbogbo ìdílé àwọn ọmọ Ṣúhámù, gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàáméjìlélọ́gbọ̀n ó lé irínwó (64,400).

44Ti àwọn ọmọ Ásérì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ímínà, ìdílé àwọn ọmọ Ímínà; ti Íṣífì, ìdílé àwọn ọmọ Íṣífì; ti Béríà, ìdílé àwọn ọmọ Béríà;

45Ti àwọn ọmọ Béríà: ti Mákíẹ́lì, ìdílé àwọn ọmọ Mákíẹ́lì.

45ti Hébérì, ìdílé àwọn ọmọ Hébérì;

46(Orúkọ ọmọ Áṣérì obìnrin nì jẹ́ Ṣérà.)

47Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Áṣérì gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbéje (53,400).

48Ti àwọn ọmọ Náfítalì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Jásélì, ìdílé àwọn ọmọ Jásélì: ti Gúnì, ìdílé àwọn ọmọ Gúnì;

49ti Jésérì, ìdílé àwọn ọmọ Jéṣérì;

49ti Ṣílémù, ìdílé àwọn ọmọ Ṣilemù.

50Wọ̀nyí ni ìdílé ti Náfítalì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbéje (45,400).

51Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́, ó lé ẹgbẹ̀sán ó dín àádọ́rin (601,730).

52OLÚWA sọ fún Mósè pé,

53“Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn

54Fún àwọn ọ̀pọ̀ ni kí ìwọ ó fún ní ogún ìlú púpọ̀ àti fún àwọn tí ó kéré ni kí ìwọ ó fi kékeré fún, ẹnìkọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ gba ogún ìbí tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí a kọ.

55Rí dájú pé ilẹ̀ yìí gbọdọ̀ jẹ́ fífi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọn sì ti pọ̀ tó. Gẹ́gẹ́ bí orúkọ ẹ̀yà àwọn baba wọn ni kí wọn kí ó ni ín.

56Olúkúlùkù ogún ìní ni a gbọdọ̀ fi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti pọ̀ tó láàrin ńlá àti kékeré.”

57ⓒ Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Léfì tí a kà nínú wọn gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Gáṣónì, ìdílé àwọn ọmọ Gáṣónì; ti Kóhátì, ìdílé àwọn ọmọ Kóhátì; ti Mérárì, ìdílé àwọn ọmọ Mérárì.

58Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Léfì; ìdílé àwọn ọmọ Hébírónì, ìdílé àwọn ọmọ Málì, ìdílé àwọn ọmọ Múṣì, ìdílé àwọn ọmọ Kórà. (Kóhátì ni baba Ámírámù,

58ìdílé àwọn ọmọ Líbínì,

59Orúkọ aya Ámírámù sì ń jẹ́ Jókébédì, ọmọbìnrin Léfì, tí ìyá rẹ̀ bí fún Léfì ní Éjíbítì. Òun sì bí Árónì, Mósè, àti Míríámù arábìnrin wọn fún Ámírámù.

60Árónì ni baba Nádábù àti Ábíhù, Élíásárì àti Ítamárì.

61Ṣùgbọ́n Nádábù àti Ábíhù kú, nígbà tí wọ́n rú ẹbọ níwájú OLÚWA nígbà tí wọ́n mú iná àjèjì wá.)

62Gbogbo àwọn ọmọkùnrin Léfì láti oṣù kan àti ju bẹ́ẹ̀ lọ ẹgbàá mọ́kànlá ó lé lẹ́gbẹ̀rún (23,000). Wọn kò ka wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tókù nítorí tí wọ́n kò gba ogún ìní lára wọn.

63Àwọn wọ̀nyí ni Mósè àti Élíásárì àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Móábù lẹ́bá odò Jọ́dánì létí Jẹ́ríkò.

64ⓓ Kò sí ẹnìkan nínú àwọn tí Mósè àti Árónì àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ihà Sínáì.

65Nítorí OLÚWA ti sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé kíkú ni wọn yóò kú sí ihà, kò sì sí ẹnìkankan nínú wọn tí kò kú à fi Kálẹ́bù ọmọ Jéfúnì, àti Jóṣúà ọmọ Núnì.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
iv>