1Gẹ́gẹ́ bí òkú eṣinṣin tí ń fún ìpara ní òórùn burúkú,bẹ́ẹ̀ náà ni òmùgọ̀ díẹ̀ ṣe ń bo ọgbọ́n àti ọlá mọ́lẹ̀.
2Ọkàn ọlọgbọ́n a máa sí sí ohun tí ó tọ̀nà,ṣùgbọ́n ọkàn òmùgọ̀ sí ohun tí kò dára.
3Kó dà bí ó ti ṣe ń rìn láàrin ọ̀nà,òmùgọ̀ kò ní ọgbọ́na sì máa fi han gbogbo ènìyàn bí ó ti gọ̀ tó.
4Bí ìbínú alákòóso bá dìde lòdì sí ọ,ma ṣe fi àyè rẹ sílẹ̀;ìdákẹ́jẹ́jẹ́ le è tu àṣìṣe ńlá.
5Ohun ibi kan wà tí mo ti rí lábẹ́ oòrùn,irú àṣìṣe tí ó dìde láti ọ̀dọ̀ alákòóso.
6A gbé aṣiwèrè sí ọ̀pọ̀ ipò tí ó ga jù lọ,nígbà tí ọlọ́rọ̀ gba àwọn àyè tí ó kéré jù lọ.
7Mo ti rí ẹrú lórí ẹṣin,nígbà tí ọmọ aládé ń fi ẹṣẹ̀ rìn bí ẹrú.
7
8Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́ kòtò, ó le è ṣubú sínú rẹ̀;ẹnikẹ́ni tí ó bá la inú ògiri, ejò le è ṣán-an.
9Ẹnikẹ́ni tí ó bá pe òkúta lẹ́jọ́ le è ní ìpalára láti ipasẹ̀ wọn;ẹnikẹ́ni tí ó bá la ìtì-igi le è ní ìpalára láti ipasẹ̀ wọn.
9
10Bí àáké bá kútí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ kò sì sí ní pípọ́nyóò nílò agbára púpọ̀ṣùgbọ́n ọgbọ́n orí ni yóò mú àṣeyọrí wá.
10
11Bí ejò bá sán ni kí a tó lo oògùn rẹ̀,kò sí èrè kankan fún olóògùn rẹ̀.
11
12Ọ̀rọ̀ tí ó wá láti ẹnu ọlọ́gbọ́n a máa ní oore-ọ̀fẹ́ṣùgbọ́n ètè òmùgọ̀ fúnrarẹ̀ ni yóò parun.
13Ìbẹ̀rẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ́ òmùgọ̀;ìparí rẹ̀ sì jẹ́ ìṣínwín búburú.
14Wèrè a sì máa ṣàfikún ọ̀rọ̀
14kò sí ẹni tí ó mọ ohun tí ó ń bọ̀ ta ni ó le è ṣọ fún-un ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀?
15Iṣẹ́ aṣiwèrè a máa dá lágbarakò sì mọ ojú ọ̀nà sí ìgboro.
15
16Ègbé ni fún ọ, ìwọ ilẹ̀ tí ọba ń ṣe ìranṣẹ́ rẹ̀àti tí àwọn ọmọ aládé ń ṣe àsè ní òwúrọ̀.
17Ìbùkún ni fún ọ, ìwọ ilẹ̀ èyí tí ọba rẹ̀ jẹ́ọmọ ọlọ́lá, àti tí àwọn ọmọ aládé ń jẹun ní àsìkò tí ó yẹ,fún ìlera, tí kì í ṣe fún ìmọ̀tí para.
17
18Bí ènìyàn bá ń lọ́ra, ilé a máa wú,bí ọwọ́ rẹ̀ bá ń ṣe ọ̀lẹ, ilé a máa jó.
18
19Ẹ̀rín rínrín ni a ṣe àṣè fún,wáìnì a máa mú ayé dùn,ṣùgbọ́n owó ni ìdáhùn sí ohun—gbogbo.
19
20Ma ṣe bú ọba, kódà nínú èrò rẹ,tàbí kí o ṣépè fún ọlọ́rọ̀ ní ibi ìbùsùn rẹ,nítorí pé ẹyẹ ojú—ọ̀run le è gbé ọ̀rọ̀ rẹẹyẹ tí ó sì ní ìyẹ́ apá le è fi ẹjọ́ ohun tí o sọ sùn.