Ìwé Sáàmù 113:1-9 BYB2014 - Bible AI

1Ẹ máa yin OLÚWA, yìn ín ẹ̀yin ìránṣẹ́ OLÚWA, ẹ yin orúkọ OLÚWA.

2Fi ìbùkún fún orúkọ OLÚWA láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.

3Láti ìlà òòrun títí dé ìwọ Rẹ̀ orúkọ OLÚWA ni kí á máa yìn.

3

4OLÚWA ga lórí gbogbo ayé, àti ògo Rẹ̀ lórí àwọn ọ̀run.

5Ta ló dàbí OLÚWA Ọlọ́run wa, tí ó gbé ní ibi gíga.

6Tí ó Rẹ ara Rẹ̀ sílẹ̀ láti wò òun tí ó ń bẹ lọ́run, àti nínú ayé!

6

7Ó gbé òtòsì dìde láti inú erùpẹ̀, àti pé ó gbé aláìní sókè láti inú ààtàn wá.

8Kí ó le mú-un jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ aládé àní pẹ̀lú àwọn ọmọ aládé àwọn ènìyàn Rẹ̀.

9Ó mú àgàn obìnrin gbé inú ilé, àti láti jẹ́ aláyọ̀ ìyá fún àwọn ọmọ Rẹ̀.

9Ẹ yin OLÚWA.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
v>