Ìwé Sáàmù 115:1-18 BYB2014 - Bible AI

1Kí ṣe fún wa, OLÚWA kì ṣe fún wá, ṣùgbọ́n fún orúkọ Rẹ̀ ní a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ Rẹ.

2Torí kí ní àwọn aláìkọlà yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà.

3Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.

4ⓐ Òrìṣà fàdákà àti wúrà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn

5Wọn ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ̀rọ̀, wọn ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.

6Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ràn: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọ́n kò fi gbóòórùn

7Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹṣẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.

8Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ Rẹ̀ lé wọn.

8

9Ìwọ Ísírẹ́lì gbẹ́kẹ̀lé OLÚWA: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn

10Ẹ yin ilé Árónì, gbẹ́kẹ̀lé OLÚWA: oun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn

11Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù OLÚWA, gbẹ́kẹ̀lé OLÚWA: oun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.

11

12OLÚWA tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Ísírẹ́lì; yóò bùkún ilé Árónì.

13ⓑ Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù OLÚWA, àti kékeré àti ńlá.

14OLÚWA yóò mú ọ pọ̀ síi síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ Rẹ̀.

15Ẹ fi ìbùkún fún OLÚWA ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.

15

16Ọ̀run àní ọ̀run ni ti, OLÚWA: ṣùgbọ́n ayé lo fi fún ọmọ ènìyàn.

17Òkú kò le yìn OLÚWA, tàbí ẹni tí o ti lọ sí ìṣàlẹ̀ ìdákẹ́jẹ́.

18Ṣùgbọ́n àwa o fi ìbùkún fún OLÚWA láti ìsinsìn yí lọ àti títí láéláé.

18Ẹ yin OLÚWA.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
iv>