Ìwé Sáàmù 12:1-8 BYB2014 - Bible AI

1Ràn wá lọ́wọ́, OLÚWA nítorí ẹni ìwà bí Ọlọ́run kò sí mọ́; Olótìítọ́ tí pòórá kúrò láàrin àwọn ènìyàn.

2Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.

2

3Kí OLÚWA kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu

4tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa: ta ni ọ̀gá wa?”

4

5“Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkéróra àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí” ni OLÚWA wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn”

6Ọ̀rọ̀ OLÚWA sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà ti a yọ́ nínú ìléru àmọ́, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.

6

7OLÚWA, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.

8Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òṣì láàrin àwọn ènìyàn.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
>