Ìwé Sáàmù 120:1-7 BYB2014 - Bible AI

1Èmi ké pe OLÚWA nínú ìpọ́njú mi, ó sì dámi lóhùn

2Gbà mí, OLÚWA, kúrò lọ́wọ́ ète èké àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.

3Kí ni kí a fi fún ọ? Àti kín kí a tún ṣe fún ọ, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?

4Òun yóò bá ọ́ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun, pẹ̀lú eyin iná igi ìgbálẹ̀.

4

5Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Mésékì, nítorí èmi gbé nínú àgọ́ Kédárì!

6Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé láàrin àwọn tí ó kóríra àlàáfíà.

7Ènìyàn àlàáfíà ni mí; ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni ti wọn.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
v>