Ìwé Sáàmù 124:1-8 BYB2014 - Bible AI

1“Ìba má ṣe pé OLÚWA tí ó ti wà fún wa” ni kí Ísírẹ́lì kí ó máa wí nísinsìn yìí;

2“Ìbá má ṣe pé OLÚWA tó wà ní tiwa,” Nígbà tí àwọn ènìyàn dúró sí wa:

3Nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láàyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wá

4Nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀

5Nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.

5

6Olùbùkún ni OLÚWA, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.

7Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.

8Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ OLÚWA, tí ó dá ọ̀run òun ayé.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
v>