1Ní ẹ̀bá odò Bábílónì, níbẹ̀ ní àwa gbé jókòó àwa sì sunkún nígbà tí àwa rántí Síónì.
2Àwa fi dùùrù wa kọ́ sí orí igi wílóò, tí ó wà láàrin Rẹ̀.
3Nítorí pé níbẹ̀ ní àwọn tí ó kó wa ní ìgbékùn bèèrè orin lọ́wọ́ wá, àti àwọn tí ó ni wá lára bèèrè ìdárayá wí pé; ẹ kọ orin Síónì kan fún wa.
4Àwa o ti ṣe kọ orin OLÚWA ni ilẹ̀ àjèjì
5Jérúsálẹ́mù, bí èmi bá gbàgbé Rẹ jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó gbàgbé ìlò Rẹ.
6Bí èmi kò bá rántí Rẹ, jẹ́ kí ahọ́n mi kí ó lẹ̀ mọ́ èrìgì mi; bí èmi kò bá fi Jérúsálẹ́mù ṣáájú olórí ayọ̀ mi gbogbo.