Ìwé Sáàmù 14:1-7 BYB2014 - Bible AI

1ⓐ  ⓑ Asiwèrè wí nínú ọkàn Rẹ̀ pé, “kò sí Ọlọ́run.” Wọ́n díbàjẹ́, iṣẹ́ wọn sì burú; kò sí ẹnìkan tí ó ṣe rere.

2OLÚWA sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run wá lórí àwọn ọmọ ènìyàn bóyá ó le rí ẹni tí òye yé, ẹnikẹ́ni tó ń wá Ọlọ́run.

3Gbogbo wọn sì ti yípadà, gbogbo wọn sì ti díbàjẹ́; kò sì sí ẹni tí ó ń ṣe rere, kò sí ẹnìkan.

3

4Ǹjẹ́ olùṣe búburú kò ha ní kọ́ ẹ̀kọ́: àwọn tí ó ń pa ènìyàn mí jẹ bí ẹníjẹ àkàrà tí wọn kò sì ké pe OLÚWA?

5Wọ́n wà níbẹ̀, tí a bò mọ́lẹ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù, nítorí OLÚWA wà ní àwùjọ àwọn olódodo.

6Ẹ̀yin olùṣe búburú ba èrò àwọn aláìní jẹ́, ṣùgbọ́n OLÚWA ni ààbò wọn.

6

7Ìgbàlà àwọn Ísírẹ́lì yóò ti Síónì wá! Nígbà tí OLÚWA bá mú ìkólọ àwọn ènìyàn Rẹ̀ padà, jẹ́ kí Jákọ́bù kí ó yọ̀, kí inú Ísírẹ́lì kí ó dùn!

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
>