Ìwé Sáàmù 16:1-11 BYB2014 - Bible AI

1Pa mí mọ́, Ọlọ́run, nítorí nínú Rẹ ni ààbò mí wà.

2Mo sọ fún OLÚWA, “ìwọ ni Ọlọ́run mi, lẹ́yìn Rẹ èmi kò ní ire kan.”

3Sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní ayé, àwọn ni ológo nínú èyí tí ayọ̀ mí wà.

4Ìṣòro àwọn wọ̀n ọn nì yóò pọ̀ síi àwọn tí ń tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn. Ẹbọ ohun mímu ẹ̀jẹ̀ wọn ni èmi kì yóò ta sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá orúkọ wọn lẹ́nu mi.

4

5OLÚWA, ni ìní mi tí mo yàn àti ago mi, ó ti pa ohun tí íṣe tèmi mọ́.

6Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára; nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.

6

7Èmi yóò yin OLÚWA, ẹni tí ó gbàmí ní ìyànjú; ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.

8ⓐ Mo ti gbé Ọlọ́run ṣíwájú mi ní ìgbà gbogbo. Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi, a kì yóò mì mí.

8

9Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀; ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,

10ⓑ nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú iṣà òkú, tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ Rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́.

11Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí; Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní ìwájú Rẹ, pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún Rẹ.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
v>