Ìwé Sáàmù 19:1-14 BYB2014 - Bible AI

1Àwọn òrun ń sọ nípa ti ògo Ọlọ́run; Àwọ̀sánmọ̀ ń sọ nípa ti iṣẹ́ ọwọ́ Rẹ̀.

2Wọ́n ń fọhùn ní ọjọ́ dé ọjọ́; wọ́n ń fi ìmọ̀ hàn ní alẹ́ dé alẹ́.

3Kò sí ohùn tàbí èdè níbi tí a kò gbé gbọ́ ìró wọn

4ⓐ Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo orílẹ̀ ayé ọ̀rọ̀ wọn títí dé òpin ilẹ̀ ayé, ó ti kọ́ àgọ́ fún oòrùn nínú àwọn ọ̀run.

5Ti o dàbí ọkọ ìyàwó tí ó ń jáde ti yàrá Rẹ̀ wá Òun yọ bí alágbára ọkùnrin tí o ń sáré ìje.

6Ìjáde lọ Rẹ̀ ni láti òpin ọ̀run wá àti àyíká Rẹ̀ sì dé ìpínlẹ̀ Rẹ̀; kò sì sí ohun tí ó pamọ́ kúrò nínú oore Rẹ̀.

6

7Pípé ni òfin OLÚWA, ó ń yí ọkàn padà. ẹ̀rí OLÚWA dánilójú, ó sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.

8Ìlànà OLÚWA tọ̀nà, ó ń fi ayọ̀ fún ọkàn. àṣẹ OLÚWA ní mímọ́, ó ń fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú.

9Ìbẹ̀rù OLÚWA mọ́, ó ń faradà títí láéláé. Ìdájọ́ OLÚWA dájú òdodo ni gbogbo wọn.

10Wọn ṣọ̀wọ́n ju gólùù lọ, ju góòlù tí o dára jùlọ. wọ́n dùn ju oyin lọ, Àti ju afárá oyin lọ.

11Nípa wọn ni a ti sí ìránṣẹ́ Rẹ̀ létí; nípa pípa wọ́n mọ́, èrè púpọ̀ ń bẹ.

11

12Ta ni o lé mọ àṣìṣe Rẹ̀? Dáríjìn mí nínú àṣìṣe mi tí ó pamọ́.

13Wẹ ìrànsẹ́ Rẹ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀ọ́n-mọ̀-dá; Má ṣe jẹ kí wọn kí ó jọba lórí mi. Nígbà náà ní èmí yóò dúró ṣinṣin, èmi yóò sì ṣe aláìlẹ́bi kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.

13

14Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti àṣàrò ọkàn mi kí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú Rẹ, Ìwọ OLÚWA, àpáta mi. àti Olùdáǹdè mi.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
v>