Ìwé Sáàmù 2:1-12 BYB2014 - Bible AI

1ⓐ Èéṣe tí àwọn orílẹ̀ èdè fi ń dìtẹ̀, àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkísí asán?

2Àwọn ọba ayé péjọ pọ̀ àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀ sí OLÚWA àti sí Ẹni àmì òróró Rẹ̀.

3Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já,” “kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”

3

4Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín; OLÚWA fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.

5Nígbà náà ni ó bá wọn wí ní ìbínú Rẹ̀ ó sì dẹ́rùba bà wọ́n ní ìrunú Rẹ̀, ó wí pé,

6“Èmi ti fi ọba mi sí ipò lórí Síónì, òkè mímọ́ mi.”

6

7ⓑ Èmi yóò sì kéde ìpinnu OLÚWA: Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí, èmi ti di baba Rẹ.

8ⓒ Béèrè lọ́wọ́ mi, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀ èdè di ìní Rẹ, òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún Rẹ.

9Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn ìwọ yóò sì rún wọn wómú wómú bí ìkòkò amọ̀”.

9

10Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọgbọ́n; ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.

11Ẹ ṣin OLÚWA pẹ̀lú ìbẹ̀rù ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.

12Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú kí ó má ba à payin run ní ọ̀nà yin, nítorí ìbínú Rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi i ṣe ibi ìsádi wọn.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
>