Ìwé Sáàmù 23:1-6 BYB2014 - Bible AI

1OLÚWA ni Olùsọ́ àgùntàn mi, èmi kì yóò ṣe aláìní.

2ⓐ Ó mú mi dùbúlẹ̀ síbi pápá oko tútù Ó mú mi lọ síbi omí dídákẹ́ rọ́rọ́;

3Ó mú ọkàn mi padà bọ̀ sípò Ó mú mi lọ sí ọ̀nà ododo nítorí orúkọ Rẹ̀.

4Bí mo tílẹ̀ ń rìn Láàrin àfonífojì òjiji ikú, èmi kì yóò bẹ̀rù ibi kan; nítorí ìwọ wà pẹ̀lú ù mi; ọ̀gọ Rẹ àti ọ̀pá à Rẹ wọ́n ń tù mi nínú.

4

5Ìwọ tẹ́ tábìlì oúnjẹ sílẹ̀ níwájú ù mi ní ojú àwọn ọ̀tá à mi; ìwọ ta òróró sí mi ní orí; ago mí sì kún àkún wọ́ sílẹ̀.

6Nítòótọ, ire àti àánú ni yóò máa tọ̀ mí lẹ́yìn ní ọjọ́ ayé è mi gbogbo, èmi yóò sì máa gbé inú ilé OLÚWA títí láéláé.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
>