2
3Ohùn OLÚWA ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, OLÚWA náà, alágbára ń bẹ lóríi omi púpọ̀.
4Ohùn OLÚWA ní agbára; ohùn OLÚWA kún fún ọláńlá.
5Ohùn OLÚWA fọ́ igi kédárì; OLÚWA náà ló fọ́ igi kédárì Lébánónì.
6Ó mú Lébánónì fo bí i ọmọ màlúù, àti Síríónì bí ọmọ àgbáǹréré.
7Ohùn OLÚWA ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà
8Ohùn OLÚWA ń mi ihà. OLÚWA mi ihà Kádéṣì.
9Ohùn OLÚWA ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀rín bí ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòòhò. àti nínú tẹ́ḿpìlì Rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé “Ògo!”