Ìwé Sáàmù 41:1-13 BYB2014 - Bible AI

1Ìbùkùn ni fún ẹni tí ó ń rò ti aláìní: OLÚWA yóò gbà á ni ìgbà ìpọ́njú.

2OLÚWA yóò dààbò bòó yóò sí pa ọkàn Rẹ̀ mọ́: yóò bùkún fún-un ni orí ilẹ̀ kò sì ní fi sílẹ̀ fún ìfẹ́ àwọn ọ̀tá Rẹ̀.

3OLÚWA yóò gbà á lórí àkéte àìsàn Rẹ̀ yóò sì mú-un padà bọ̀ sípò kúrò nínú àìsàn Rẹ̀.

3

4Ní ti èmi, mo wí pé “OLÚWA, ṣàánú fún mí; wò mí sàn, nítorí pé mo ti ṣẹ̀ sí ọ”.

5Àwọn ọ̀ta mi ń sọ́rọ̀ mi nínú arankan, pé “Nígbà wo ni yóò kú ti orúkọ Rẹ̀ yóò sì run?”

6Nígbà kígbà tí ẹnìkan bá wá wò mí, wọn ń sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn, nígbà tí àyà Rẹ̀ bá kó ẹ̀ṣẹ̀ jọ sí ara Rẹ̀; nígbà tí ó bá jáde lọ yóò sì máa tàn án kalẹ̀.

7Àwọn ọ̀tá mi gbìmọ̀ papọ̀ nípa mi; èmi ni wọn ń gbìmọ̀ ibi sí,

8wọ́n wí pé “Ohun búburú ni ó di mọ́-ọn sinsin àti ní ibi tí ó dùbúlẹ̀ sí, kì yóò dìde mọ́”.

9ⓐ Pàápàá ọ̀rẹ́ mi tímọ́tímọ́, ẹni tí mo gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó ń jẹ nínú oúnjẹ mi, tí gbé gìgíṣẹ̀ Rẹ̀ sókè sí mi.

9

10Ṣùgbọ́n ìwọ OLÚWA, ṣàánú fún mi; gbé mi sókè, kí ń ba lè san fún wọn.

11Èmi mọ̀ pé inú Rẹ̀ dùn sí mi, nítorí ọ̀tá mi kò borí mi.

12Bí ó ṣe tèmi ni ìwọ dì mí mú nínú ìwà òtítọ́ mi ìwọ sì gbé mi kalẹ̀ níwájú Rẹ títí láé.

12

13Olùbùkún ni OLÚWA, Ọlọ́run Ísírẹ́lì láé àti láéláé. Àmín àti Àmín.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
v>