Ìwé Sáàmù 45:1-17 BYB2014 - Bible AI

1Ọkàn mi mọ ọ̀rọ̀ rere gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń sọ ohun tí mo ti ṣe fún ọba ahọ́n mi ni kálámù ayára kọ̀wé.

2Ìwọ yanjú ju àwọn ọmọ ènìyàn lọ: a da oore-ọ̀fẹ́ sí ọ ní ètè: nítorí náà ni Ọlọ́run ṣe bùkún fún ọ láéláé.

3Gba idà Rẹ mọ́ ìhà Rẹ, ìwọ alágbára jùlọ wọ ara Rẹ̀ ní ògo àti ọla ńlá.

4Nínú ọlá-ńlá Rẹ máa gẹṣin lọ ní àlàáfíà lórí òtítọ́, ìwà tútù àti òtítọ́ jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún Rẹ ṣe ohun ẹ̀rù

5Jẹ́ kí ọfà mímú Rẹ̀ dá ọkàn àwọn ọ̀tá ọba lu jẹ́ kí àwọn orílẹ̀ èdè ṣubú sí abẹ́ ẹsẹ̀ Rẹ̀

6ⓐ Ìjọba Rẹ Ọlọ́run, yóò pẹ́ títí ayé ọ̀pá aládé ni yóò jẹ́ ọ̀pá ìjọba Rẹ

7Ìwọ fẹ́ olódodo, ìwọ sì kórìíra ìwà búburú nígbà náà Ọlọ́run, Ọlọ́run Rẹ̀ ti yàn ọ́ ṣe olórí àwọn ẹlẹgbẹ́ Rẹ̀, nípa fífí àmì òróró ayọ̀ kùn ọ́

8Gbogbo aṣọ Rẹ̀ ni ó ń rùn pẹ̀lú òjíá àti alóe àti kaṣíà; láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe orin olókùn tẹ́ẹ́rẹ́ mú inú Rẹ̀ dùn.

9Àwọn ọmọbìnrin àwọn aládé wà nínú àwọn àyànfẹ́ Rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún Rẹ̀ ni ayaba náà gbé dúró nínú wúrà ófórì.

9

10Gbọ́ ìwọ ọmọbìnrin, ronú kí o sì dẹtí Rẹ̀ sími gbàgbé àwọn ènìyàn Rẹ àti ilé baba Rẹ

11Bẹ́ẹ̀ ni ọba yóò fẹ́ ẹwà Rẹ gidigidi nítorí òun ni OLÚWA Rẹ kí ìwọ sì máa tẹríba fún un.

12Ọmọbìnrin ọba tirẹ̀ yóò wá pẹ̀lú ẹ̀bùn àwọn ọkùnrin ọlọ́rọ̀ yóò máa wá ojú rere Rẹ̀.

12

13Gbogbo ògo ni ti ọmọbìnrin ọba ní àárin ilé Rẹ̀ aṣọ ìbalẹ̀ Rẹ̀ a ṣe é lọ́sọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà

14Nínú aṣọ ìbànújẹ́ iyebíye ni a mú-un wá sí ọ̀dọ̀ ọba àwọn wúndíá ẹgbẹ́ Rẹ̀ tẹ̀ lé e wọ́n, sí mú-un tọ̀ ọ́ wá

15Wọ́n sì mú un wá pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn wọ́n sì wọ ààfin ọba.

15

16Ọmọ Rẹ̀ ni yóò gba ipò baba Rẹ̀ ìwọ yóò sì fi wọ́n joyè lórí ilẹ̀ gbogbo.

17Èmí yóò máa rántí orúkọ Rẹ̀ ní ìran gbogbo nígbà náà ni orílẹ̀ èdè yóò yìn ọ́ láé àti láéláé.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
v>