1Ẹni ńlá ní OLÚWA, tí o sì yẹ láti máa yìn ní ìlú Ọlọ́run wa, lórí òkè mímọ́ Rẹ̀
2ⓐ Ó dára nínú ipò ìtẹ́ Rẹ̀ ayọ̀ gbogbo ayé òkè Síónì, ní ìhà àríwá ní ìlú ọba ńlá.
3Ọlọ́run wà nínú ààbò ààfin Rẹ̀; ó fi ara Rẹ̀ hàn láti jẹ́ odi alágbára.
4Nígbà tí àwọn ọba kógun jọ pọ̀ wọ́n jùmọ̀ ń kọjá lọ
5Wọn ríi bẹ́ẹ̀ ni ẹnu sì yà wọ́n a yọ wọ́n lẹ́nu, wọ́n yára lọ
6Ẹ̀rù sì bà wọ́n níbẹ̀ ìrora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó wà nínú ìrọbí
7Ìwọ bà wọ́n jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọkọ̀ orí omi Táṣíṣì wọ́n fọ́nká láti ọwọ́ ìjì ìlà oorùn.