1Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ Rẹ: dá mi láre nípa agbára Rẹ.
2Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run; fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
3Àwọn àlejò ń dìde sí mí. Àwọn aláìláàánú ènìyàn ń wá ayé mi àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.
3
4Kíyèsí i Ọlọ́run ni Olùrànlọ́wọ́ mi; OLÚWA ní ẹni tí ó mú mi dúró, pa wọ́n run nínú òtítọ́ Rẹ.
4
5Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi; pa wọ́n run nínú òtítọ́ Rẹ.
5
6Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ èmi yóò yin orúkọ Rẹ, OLÚWA, nítorí tí ó dára.
7Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo ojú mi ti wo ìborí lórí ọ̀ta mi.