1Ìwọ tí kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká ìwọ ti bínú nísìnsín yìí, tún ara Rẹ yípadà sí wá.
2Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ Rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mi.
3Ìwọ ti fi ìgbà ewu hàn àwọn ènìyàn Rẹ; Ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wa gbọ́n-ọ́ngbọ́n-ọ́n.
3
4Àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ̀ ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fíhàn nítorí òtítọ́.
4Sela
5ⓐ Fi ọwọ́ ọ̀tún Rẹ̀ gbà wá kí ó sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
6Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ Rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pín ṣèkémù jáde èmi o sì wọ̀n àfonífojì ṣúkótù.
7Tèmi ni Gílíádì, tèmi sì ni Mánásè; Éfúráímù ni àsìbórì mi, Júdà sì ní ọ̀pá àṣẹ mi.
8Móábù ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Édómù ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí fìlísitinì ni mo kígbe ayọ̀.”
8
9Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Édómù?
10Kí ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
11Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ní ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
12Nípa Ọlọ́run ni a ó ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ̀ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.