Ìwé Sáàmù 61:1-8 BYB2014 - Bible AI

1Gbọ́ ẹkún mi, Ọlọ́run; Tẹ́tí sí àdúrà mi.

2Láti òpin ayé wá ni èmi yóò pè ọ́, mo pè nígbà àyà mi ń ṣàárẹ̀; mú mi lọ sí ibi àpáta tí ó ga jù mí lọ.

3Nítorí ìwọ ti jẹ́ ibi ààbò mi, ilé ìsọ́ agbára àwọn ọ̀tá.

3

4Mo ń lépa láti máa gbé nínú àgọ́ Rẹ títí láé kí ń sì rí ààbò níbi ìyẹ́ apá Rẹ.

5Nítorí ìwọ ti gbọ́ àwọn ẹ̀jẹ́ mi, Ọlọ́run; Ìwọ ti fún mi ní ogún àwọn tí ó bẹ̀rù orúkọ Rẹ̀.

5

6Jẹ́ kí ẹ̀mí ọba kí o gùn, ọdùn Rẹ̀ fún ìrandíran.

7Kí o máa jọba níwájú Ọlọ́run títí láé; pèsè àánú àti òtítọ́ Rẹ̀ tí yóò máa ṣe ìtọ́ju Rẹ.

7

8Nígbà náà ni èmi ó máa kọrin ìyìn sí orúkọ Rẹ títí láé kí ń san ẹ̀jẹ́ mí ní ojoojúmọ́.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
>