Ìwé Sáàmù 63:1-11 BYB2014 - Bible AI

1Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi, nígbà gbogbo ní mo ń ṣàfẹ́rí Rẹ óùngbẹ́ Rẹ ń gbẹ ọkàn mi ara mi fà sí ọ, ní ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ ti ń ṣàárẹ̀ níbi tí kò sí omi

2Èmi ti rí ọ ní ibi mímọ́ mo rí agbára àti ògo Rẹ.

3Nítorí ìfẹ́ Rẹ dára ju ayé lọ, ètè mi yóò fògo fún ọ.

4Èmi o yìn ọ́ níwọ̀n ìgbà tí mo wà láàyè, èmi ó gbé ọwọ́ sókè, èmi ó sì pe orúkọ Rẹ.

5A ó tẹ́ ọkàn mi lọ́rùn bí ọlọ́ràá oúnjẹ; pẹ̀lú ètè ìyìn, ẹnu mi yóò yìn ọ.

5

6Nígbà tí mo rántí Rẹ lórí ìbusùn mi; èmi ń ronú Rẹ títí iṣọ́ òru.

7Nítorí ìwọ ni ìrànlọ́wọ́ mi, mo kọrin níbi òjijì-ìyẹ́ apá Rẹ.

8Ọkàn mí fà sí ọ: ọwọ́ ọ̀tún Rẹ gbé mi ró.

8

9Àwọn tí ó ń wá ọkàn mí ní a ó parun; wọn o sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìṣàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.

10Wọn ó ti ọwọ́ idà ṣubú wọn ó sì di jíjẹ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.

10

11Ṣùgbọ́n ọba yóò yọ̀ nínú Ọlọ́run ẹni tí o fi orúkọ Ọlọ́run búra yóò sògo ṣùgbọ́n ẹnu àwọn òpùrọ́ la ó pa mọ́.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
v>