Ìwé Sáàmù 67:1-7 BYB2014 - Bible AI

1Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa kí o sì bùkún fún wa kí ó sì jẹ́ kí ojú Rẹ̀ tàn yí wa ká,

2kí ọ̀nà Rẹ̀ le di mímọ̀ ní ayé, ìgbàlà Rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀ èdè.

3Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run; kí gbogbo ènìyàn kí o yìn ọ!

4Kí orílẹ̀ èdè kí o yọ̀, kí o sì kọrin fún ayọ̀, nítorí ìwọ fi òdodo darí àwọn ènìyàn ìwọ si jọba àwọn orílẹ̀-èdè ní ayé.

5Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run; kí gbogbo ènìyàn kí ó yìn ọ́.

5Sela

6Nígbà náà ní ilẹ̀ yóò mú ìkórè Rẹ̀ wá, Ọlọ́run, Ọlọ́run wa yóò bùkún fún wa.

7Ọlọ́run yóò bùkún fún wa, àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò sì máa bẹ̀rù Rẹ̀.

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide
>