1Ní Júdà ni a mọ Ọlọ́run; orúkọ Rẹ̀ sì lágbára ní Ísírẹ́lì
2Àgọ́ Rẹ̀ wà ní Sálẹ́mù, ibùgbé Rẹ̀ ní Síónì.
3Níbẹ̀ ní o ṣẹ́ ọfà, asà àti àwọn idà, ohun ìjà ogun.
3Sela
4Iwọ ni ògo àti ọlá Ju òkè-ńlá íkogun wọ̀nyìí lọ.
5Àwọn akíkanjú ọkùnrin A kó àwọn akíkanjú ogun ní ìkógun wọn sún oorun ìgbẹ̀yìn wọn; kò sí ọ̀kan nínú àwọn ajagun tó lè gbé ọwọ́ Rẹ̀ sókè.
6Ní ìfìbú Rẹ, Ọlọ́run Jákọ́bù, àwọn ẹsin àti kẹ̀kẹ́ ogun sì dúbúlẹ̀ ṣíbẹ̀.
7Ìwọ nìkan ni o yẹ kí a bẹ̀rù. Ta ló lé dúró níwájú Rẹ nígbà tí ìwọ bá ń bínú?
8Ìwọ ń ṣe ìdàjọ́ láti ọ̀run, ilé ayé bẹ̀rù, ó sì dúró jẹ́ ẹ́:
9Nígbà tí, ìwọ Ọlọ́run, bá dìde láti ṣe ìdájọ́, láti gba àwọn ẹni ìnílára ilẹ̀ náà.