Ìwé Sáàmù 8:1-9 BYB2014 - Bible AI

1OLÚWA, OLÚWA wa, orúkọ Rẹ̀ ti tó tóbi tó ní gbogbo àyé! Ìwọ ti gbé ògo Rẹ̀ ga ju àwọn ọ̀run lọ.

2ⓐ Láti ẹnu ọmọ ọwọ́ àti ọmọ ọmú ni o ti yan ìyìn nítorí àwọn ọ̀ta Rẹ, láti pa àwọn ọ̀ta àti àwọn olùgbẹ̀san lẹ́nu mọ́.

2

3Nígbà tí mo ro ọ̀run Rẹ, iṣẹ́ ìka Rẹ, òṣùpá àti ìràwọ̀, tí ìwọ tí gbé kalẹ̀,

4kí ni ènìyàn tí ìwọ ń rò nípa Rẹ̀, ọmọ ènìyàn tí ìwọ ń ṣe ìtọ́jú Rẹ̀?

5Ìwọ ṣeé ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju ẹ̀dá ọ̀run lọ ìwọ sì dée ní adé ògo àti ọlá.

5

6Ìwọ mu-un jọba lórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ Rẹ; ìwọ si fi ohun gbogbo sí abẹ́ ẹsẹ̀ Rẹ̀:

7gbogbo ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran, àti ẹranko ìgbẹ́,

8ẹyẹ ojú ọrun, àti ẹja inú òkun, àti ohun tí ń wẹ nínú ipa òkun.

8

9OLÚWA, OLÚWA wa, Orúkọ Rẹ̀ ti ní ìyìn tó ní gbogbo ayé!

Copyright © 2014 by Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide