1OLÚWA jọba, jẹ́ kí ayé kí o yọ̀ jẹ́ kí inú ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù kí ó dùn
2Ojú ọ̀run àti òkùnkùn yí ká òdodo àti ìdájọ́ ni ó ṣe ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìtẹ́ Rẹ̀.
3Iná ń jó níwájú Rẹ̀. O sì ń jó àwọn ọ̀ta Rẹ̀ yíká kiri
4Ìmọ́lẹ̀ Rẹ̀ tàn ó sí kárí ayé ayé rí i ó sì wárìrì
5Òkè gíga yọ́ gẹ́gẹ́ bí ìda níwájú OLÚWA, níwájú OLÚWA gbogbo ayé.
6Àwọn ọ̀run ròyìn òdodo Rẹ̀, gbogbo ènìyàn sì rí ògo Rẹ̀.
6
7ⓐ Gbogbo àwọn tí ń sin òrìṣà ni ojú yóò ti, àwọn ti n fi ère ṣe àfẹ́rí ara wọn Ẹsìn ín, ẹ̀yin òrìṣà;
8Síónì gbọ́, inú Rẹ̀ sì dùn ìnú àwọn ilé Júdà sì dùn Nítorí ìdájọ́ Rẹ, OLÚWA
9Nítorí pé ìwọ, OLÚWA, ní ó ga ju gbogbo ayé lọ ìwọ ni ó ga ju gbogbo òrìsà lọ.
9
10Jẹ kí gbogbo àwọn tí ó fẹ́ OLÚWA, kórira ibi, ó pa ọkan àwọn ènìyàn mímọ́ Rẹ̀ mọ́ ó gbà wọ́n ní ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú.
11Ìmọ́lẹ̀ tàn sórí àwọn olódodo àti ayọ̀ nínú àlàyé ọkàn
12Ẹ yọ̀ nínú OLÚWA, ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olódodo, kí ẹ sì yin orúkọ Rẹ̀ mímọ́.