Ìwé Wòlíì Àìsáyà 21:1-17 BYB2014 - Bible AI

1Ọ̀rọ̀ ìmọ̀ tí ó kan ihà lẹ́bàá òkun: Gẹ́gẹ́ bí ìjì líle ti í jà kọjá ní ilẹ̀ ní gúṣù, akógunjàlú kan wá láti ihà, láti ilẹ̀ ìpayà.

2Ìran tí a ń fojú ṣọ́nà fún ni a ti fi hàn mí ọlọ̀tẹ̀ ti tasírí, fọ́lé fọ́lé ti kẹ́rù. Élámù kojújà! Mẹ́díà ti tẹ̀gùn! Èmi yóò mú gbogbo Ìpayínkeke dópin, ni ó búra.

2

3Pẹ̀lú èyí, ìrora kómi lára gírígírí, ìrora gbámimú, gẹ́gẹ́ bí i ti obìnrin tí ń rọbí, Mo ta gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n nítorí ohun tí mo gbọ́, ọkàn mi pòrúúrù nípa ohun tí mo rí.

4Ọkàn mí dàrú, ẹ̀rù mú jìnnìjìnnì bá mi, tanmọóko tí mo ti ń fẹ́ ẹ́ rí ti wá di ìpayà fún mi.

4

5Wọ́n tẹ́ tábìlì, wọ́n tẹ́ ẹní àtẹ́ẹ̀ká, wọ́n jẹ, wọ́n mu! Dìde nílẹ̀, ẹ̀yin òṣìṣẹ́, ẹ kún aṣà yín!

6Èyí ni ohun tí OLÚWA sọ fún mi: “Lọ, kí o bojúwòde kí o sì jẹ́ kí ó wá sọ ohun tí ó rí.

7Nígbà tí ó bá rí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin, àwọn agun-kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí àwọn tí ó gun ràkúnmí, jẹ́ kí ó múra sílẹ̀, àní ìmúra gidigidi.”

8Báyìí ni alóre náà kígbe, “Láti ọjọ́ dé ọjọ́, OLÚWA mi, mo dúró ní ilé ìṣọ́, alaalẹ́ ni mo fi ń wà nípò mi.

9Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀wá yìí nínú kẹ̀kẹ́ ogun àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin. Ó sì mú ìdáhùn padà wá: ‘Bábílónì ti ṣubú, ó ti ṣubú! Gbogbo àwọn ère òrìṣàa rẹ̀ ló fọ́nká lórí ilẹ̀!’”

9

10Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gúnmọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà, mo sọ ohun tí mo ti gbọ́ láti ọ̀dọ̀ OLÚWA àwọn ọmọ-ogun, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Ísírẹ́lì.

11Ọ̀rọ̀ ìmọ̀ tí ó kan Dúmáhì: Ẹnìkan ké sí mi láti Séírì wá “Alóre, kí ló kù nínú òru náà?”

12Alóre náà dáhùn wí pé, “Òwúrọ̀ súnmọ́tòsí, àti òru náà pẹ̀lú. Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrè kí o sì tún dẹ̀yìn padà wá.”

13Ọ̀rọ̀ ìmọ̀ tí ó kan Arábíyà: Ẹ̀yin ẹgbẹ́ èrò ti Dídánítì, tí ó pàgọ́ sínú igbó Arábíyà,

14gbé omi wá fún àwọn tí òùngbẹ ń gbẹ; ẹ̀yin tí ó ń gbé Tẹ́mà, gbé oúnjẹ wá fún àwọn ìsáǹsá.

15Wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ idà, kúrò lọ́wọ́ idà tí a fàyọ, kúrò lọ́wọ́ ọrun tí ó lò àti kúrò nínú ìgbóná ogun.

16Èyí ni ohun tí OLÚWA sọ fún mi: “Láàrin ọdún kan, gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ọgbà, í ti í kà á, gbogbo ayẹkẹ Kédárì yóò wá sí òpin.

17Àwọn tafàtafà tí ó ṣálà, àwọn jagunjagun Kédárì kò ní tó nǹkan” OLÚWA, Ọlọ́run Ísírẹ́lì ni ó ti sọ̀rọ̀.

le>