Ìwé Wòlíì Àìsáyà 37:1-38 BYB2014 - Bible AI

1Nígbà tí ọba Heṣekáyà gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹ́ḿpìlì OLÚWA lọ.

2Òun sì rán Eliákímù alákoṣo ààfin, Ṣébínà akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ Wòlíì Àìṣáyà ọmọ Ámósì.

3Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Heṣekáyà sọ: ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ìtìjú gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ọmọdé kùdẹ̀dẹ̀ ìbí tí kò sì sí agbára láti bí wọn.

4Ó lè jẹ́ pé OLÚWA Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Ásíríà ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí OLÚWA Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láàyè.”

5Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Heṣekáyà dé ọ̀dọ̀ Àìṣáyà,

6Àìṣáyà sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí OLÚWA sọ nìyìí: Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Ásíríà tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀ òdì sí mi.

7Tẹ́tísílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀ èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’ ”

8Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Áṣíríà ti fi Lákísì sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Líbínà jà.

9Ní àkókò yìí Ṣenakérúbù gbọ́ ìròyìn kan pé Tíhákà ará Kúṣì ọba Éjíbítì ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Heṣekáyà pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí:

10“Ẹ sọ fún Heṣekáyà ọba Júdà pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘a kì yóò jọ̀wọ́ Jérúsálẹ́mù fún ọba Ásíríà.’

11Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Ásíríà ti ṣe sí àwọn orílẹ̀ èdè, tí ó pa wọ́n run pátapáta. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?

12Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀ èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gósénì, Háránì, Résípì àti àwọn ènìyàn Ẹ́dẹ́nì tí wọ́n wà ní ìlú Áṣárì?

13Níbo ni ọba Hámátì wà, ọba Ápádì, ọba Ìlú Ṣefáfíámù tàbí Hénà tàbí Ífà?”

14Heṣekáyà gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹ́ḿpìlì OLÚWA ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú OLÚWA.

15Heṣekáyà sì gbàdúrà sí OLÚWA:

16OLÚWA àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, tí ó gúnwà láàrin àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lóríi gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.

17Tẹ́tí sílẹ̀, Ìwọ OLÚWA, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ OLÚWA, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Ṣenakérúbù rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.

18“Òtítọ́ ni ìwọ OLÚWA pé àwọn ọba Ásíríà ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.

19Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.

20Nísinsìn yìí, Ìwọ OLÚWA, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ọ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, OLÚWA ni Ọlọ́run.”

21Lẹ́yìn náà Àìṣáyà ọmọ Ámósì rán iṣẹ́ kan sí Heṣekáyà: “Èyí ni ohun tí OLÚWA, Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ pé: Nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Ṣenakérúbù ọba Áṣíríà,

22èyí ni ọ̀rọ̀ tí OLÚWA ti sọ nípa rẹ̀:

22“Wúndíá ọmọbìnrin Ṣíhónì kẹ́gàn ó sì fi ọ ṣe yẹ̀yẹ́. Ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù mi oríi rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.

23Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀ òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì!

24Nípa àwọn oníṣẹ́ rẹ ìwọ ti mú àbùkù bá OLÚWA. Ìwọ sì ti sọ wí pé ‘pẹ̀lú àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin mi Èmi ti gun orí òkè ńlá ńlá, ibi gíga jùlọ ti Lébánónì. Èmi ti gé igi kédárì rẹ tí ó ga jùlọ lulẹ̀, àti àyànfẹ́ igi páínì. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.

25Èmi ti gbẹ́ kàǹga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹṣẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Éjíbítì.’

25

26“Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́ tipẹ́ ni mo ti fìdíi rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta

27Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbà ṣókè.

27

28“Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sími.

29Nítorí pé inú rẹ ru sími àti nítorí pé oríkunkun rẹ ti dé etíìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.

30“Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ Ìwọ Heṣekáyà: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnraà rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara ìyẹn. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èṣo wọn.

31Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́ku láti ilé Júdà yóò ta gbòǹgbò níṣàlẹ̀ yóò sì ṣo èṣo lókè.

32Nítorí láti Jérúsálẹ́mù ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Ṣíhónì ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara OLÚWA àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.

33“Nítorí náà, èyí ni ohun tí OLÚWA wí nípa ọba Ásíríà: “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájúu rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.

34Nípa ọ̀nà tí ó gbàwá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni OLÚWA wí.

35“Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbàá là, nítorí mi àti nítoríì Dáfídì ìránṣẹ́ mi!”

36Lẹ́yìn náà ni ańgẹ́lì OLÚWA jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Ásíríà. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!

37Nítorí náà Ṣenakérúbù ọba Ásíríà fọ́ bùdó ó sì pẹṣẹ̀dà. Òun sì padà sí Nínéfè, ó sì dúró síbẹ̀.

38Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹ́ḿpìlì Níṣírókì òrìṣà rẹ, àwọn ọmọ rẹ̀ Adiramélékì àti Ṣáréṣà gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sá lọ sí ilẹ̀ Árárátì. Bẹ́ẹ̀ ni Ẹsahadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

le>