Ìwé Wòlíì Àìsáyà 56:1-12 BYB2014 - Bible AI

1Ohun tí OLÚWA wí nìyìí: “Ẹ pa ìdájọ́ mọ́ ẹ sì ṣe ohun tí ó tọ̀nà, nítorí ìgbàlà mi súnmọ́ tòsí àti òdodo mi ni a ó fi hàn láìpẹ́ jọjọ.

2Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó ṣe èyí, ọkùnrin náà tí ó dì í mú ṣinṣin, tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bàá jẹ́, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi ṣíṣe.”

2

3Má ṣe jẹ́ kí àjèjì kan tí ó ti di ara rẹ̀ mọ́ OLÚWA sọ wí pé, “OLÚWA yóò yà mí ṣọ́tọ̀ kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.” Àti kí ìwẹ̀fà kí ìwẹ̀fà kan ṣe àròyé pé “Igi gbígbẹ lásán ni mí.”

4Nítorí pé ohun tí OLÚWA wí nìyìí: “Sí àwọn ìwẹ̀fà yìí tí ó pa ọjọ́ ìsinmi mi mọ́, tí wọ́n yan ohun tí ó dùn mọ́ mi tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin

5fún wọn ni Èmi yóò fún nínú tẹ́ḿpìlì àti àgbàlá rẹ̀ ìrántí kan àti orúkọ kan tí ó sànju àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin Èmi yóò fún wọn ní orúkọ ayérayé tí a kì yóò ké kúrò.

6Àti àwọn àjèjì tí ó ṣo ara wọn mọ́ OLÚWA láti sìn ín, láti fẹ́ orúkọ OLÚWA àti láti foríbalẹ̀ fún un gbogbo àwọn tí ń pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ láì bà á jẹ́ àti tí wọ́n sì di májẹ̀mú mi mú ṣinṣin—

7ⓐ àwọn wọ̀nyí ni èmi yóò mú wá òkè mímọ́ mi èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀ nínú ilé àdúrà mi. Ọrẹ síṣun àti ẹbọ wọn ni a ó tẹ́wọ́gbà lóríi pẹpẹ mi; nítorí a ó máa pe ilé mi ní ilé àdúrà fún gbogbo orílẹ̀ èdè.”

8OLÚWA àwọn ọmọ-ogun sọ wí pé— ẹni tí ó kó àwọn àtìpó Ísírẹ́lì jọ: “Èmi yóò kó àwọn mìíràn jọ pẹ̀lúu wọn yàtọ̀ sí àwọn tí a ti kó jọ.”

9Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin ẹranko inú un pápá, ẹ wá jẹ àwọn ẹranko inú igbó run!

10Àwọn olùṣọ́ Ísírẹ́lì fọ́jú, gbogbo wọn ṣe aláìní ìmọ̀; Gbogbo wọn jẹ́ adití ajá, wọn kò lè gbó; wọ́n sùn sílẹ̀ wọ́n ń lálàá, wọ́n fẹ́ràn láti máa sùn.

11Wọ́n jẹ́ àwọn ajá tí ó kúndùn púpọ̀; wọn kì í ní ànító. Wọ́n jẹ́ olùṣọ́ àgùntàn tí kò ní òye; olúkúlùkù ń yà sọ́nà ara rẹ̀, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn sì wá ère tirẹ̀.

12“Wá,” ni igbe ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn, “fún mi ní ọtí wáìnì! Jẹ́ kí a mu ọtí bíà wa lámu yó ọ̀la yóò sì dàbí òní, tàbí kí ó dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.”

le>