Ìwé Wòlíì Àìsáyà 8:1-22 BYB2014 - Bible AI

1OLÚWA sọ fún mi pé, mú ìwé ńlá kan, kí o sì fi pẹ́ẹ́nì lásán kọ Maha-Ṣalali-Haṣi-Baṣì:

2Èmi yóò sì pe Hùráyà, Àlùfáà àti Ṣekaráyà ọmọ Jébérékíà gẹ́gẹ́ bí ẹlẹ́rìí tí ó ṣeé gbọ́kànlé fún mi.

3Lẹ́yìn náà, mo lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì-obìnrin náà, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. OLÚWA sì wí fún mi pé, “pe orúkọ rẹ̀ ní Maha-Ṣalali-Haṣi-Baṣì.

4Kí ọmọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń sọ pé ‘Baba mi’ tàbí ‘Ìyá mi’ gbogbo ọrọ̀ Dámásíkù àti ìkógun ti Ṣamáríà ni ọba àwọn Áṣíríà yóò ti kó lọ.”

5OLÚWA sì tún sọ fún mi pé:

6Nítorí pé àwọn ènìyàn ti kọ omi Ṣílóà tí ń ṣàn jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́ tí wọ́n sì láyọ̀ lórí Réṣínì àti ọmọ Rẹ̀málíà,

7fún ìdí èyí, OLÚWA fẹ́ mú wá sóríi wọn agbára ìkún omi odò ọba Ásíríà àti ògo rẹ̀ yóò sì bo gbogbo àyasíi rẹ̀ gbogbo bèbè di bíbò mọ́lẹ̀

8yóò sì gbá rìẹrìẹ dé Júdà, a gba orí ẹ̀ lọ, yóò gba ibẹ̀ lọ yóò sì mú un dọ́run. Ìyẹ́ apá rẹ̀ tí ó nà yóò bo gbogbo ìbú ilẹ̀ náà Ìwọ Ìmánúẹ́lì.

8

9Ké ariwo ogun, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè, kí a sì fọ́ọ yín túútúúú, fetísílẹ̀, ẹ̀yin ilẹ̀ jínjìn réré. Ẹ palẹ̀mọ́ fún ogun, kí a sì fọ́ ọ túútúúú!

10Ẹ hun ète yín, yóò di títúká. Ẹ gbérò ètò náà, ṣùgbọ́n kì yóò dúró, nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lúu wa.

11OLÚWA bá mi sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ̀ lórí mi pẹ̀lú ìkìlọ̀ fún mi pé, èmi kò gbọdọ̀ tẹ̀lé ọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Ó wí pé:

12ⓐ “Má ṣe pe éyí ní ọ̀tẹ̀ ohun gbogbo tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá pè ní ọ̀tẹ̀, má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n bá bẹ̀rù, má sì ṣe fòyà rẹ̀.

13OLÚWA àwọn ọmọ-ogun ni Ẹni tí ìwọ yóò kà sí mímọ́, Òun ni kí o bẹ̀rù Òun ni kí àyà rẹ̀ fò ọ́,

14ⓑ Òun yóò sì jẹ́ ibi mímọ́ ṣùgbọ́n fún ilé Ísírẹ́lì méjèèjì ni yóò jẹ́, òkúta tí í mú ni kọṣẹ̀ àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú àti fún àwọn ènìyàn Jérúsálẹ́mù ni yóò jẹ́ tàkúté àti ẹ̀bìtì.

15Ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ni yóò kọṣẹ̀, wọn yóò ṣubú wọn yóò sì fọ́ yángá, okùn yóò mú wọn, ọwọ́ yóò sì tẹ̀ wọ́n.”

15

16Di májẹ̀mú náà kí o sì fi èdìdì di òfin náà láàrin àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mi.

17ⓒ Èmi yóò dúró de OLÚWA, ẹni tí ó ń fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún ilé Jákọ́bù. Mo fi ìgbẹ́kẹ̀lé mi sínú rẹ.

18Èmi nìyí, àti àwọn ọmọ tí OLÚWA fi fún mi. Àwa jẹ́ àmì àti àpẹẹrẹ ní Ísírẹ́lì láti ọ̀dọ̀ OLÚWA àwọn ọmọ-ogun, ẹni tí ó ń gbé ní òké Síhónì.

19Nígbà tí àwọn ènìyàn bá sọ fún un yín pé kí ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn abókúsọ̀rọ̀ àti àwọn Oṣó, ti máa ń kún tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ǹjẹ́ kò ha yẹ kí àwọn ènìyàn béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run wọn bí? Èéṣe tí ẹ fi ń bá òkú sọ̀rọ̀ ní orúkọ alààyè?

20Sí òfin àti májẹ̀mú! Bí wọn kò bá sọ̀rọ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ yìí, wọn kò ní ìmọ́lẹ̀ ọjọ́.

21Pẹ̀lú ìpọ́njú àti ebi, ni wọn yóò máa rin ilẹ̀ náà ká, nígbà tí ebi bá pa wọ́n, nígbà yìí ni inú yóò bí wọn, wọn yóò síjú wòkè, wọn yóò sì ṣépè lé àwọn ọba àti ọlọ́run wọn.

22Nígbà náà ni wọn yóò síjú wolẹ̀, wọn yóò sì rí ìpọ́njú, òkùnkùn àti ìpòrúúrù tí ó bani lẹ́rù, a ó sì sọ wọ́n sínú òkùnkùn biribiri.

e>