Ìwé Wòlíì Àìsáyà 9:1-21 BYB2014 - Bible AI

1ⓐ Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀, kò ní sí ìpòrúurù kan kan mọ́ fún àwọn tí ó wà nínú ìbànújẹ́. Nígbà kan rí ó rẹ ilẹ̀ Sẹbúlúnì sílẹ̀ àti ilẹ̀ Nápítalì pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ iwájú, yóò bu ọ̀wọ̀ fún Gálílì ti àwọn aláìkọlà, ní ọ̀nà òkun, ní ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ Jọ́dánì.

2Àwọn ènìyàn tí ń rìn nínú òkùnkùn ti rí ìmọ́lẹ̀ ńlá; Lórí àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ òjìji ikú ni ìmọ́lẹ̀ ti ràn.

3Ìwọ ti sọ orílẹ̀-èdè di ńlá; wọ́n sì yọ̀ níwájúu rẹ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ti í yọ ayọ̀ ìkóórè, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ti í yọ̀ nígbà tí à ń pín ìkógun.

4Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí a ṣẹ́gun Mídíánì, ìwọ ti fọ́ ọ túútúúú àjàgà ti ń pa wọ́n lẹ́rù, ọ̀pá tí ó dábùú èjìká wọn, ọ̀gọ aninilára wọn.

5Gbogbo bàtà jagunjagun tí a ti lò lójú ogun àti gbogbo ẹ̀wù tí a yí nínú ẹ̀jẹ̀, ni yóò wà fún ìjóná, àti ohun èlò iná dídá.

6Nítorí a bí ọmọ kan fún wa, a fi ọmọkùnrin kan fún wa, ìjọba yóò sì wà ní èjìkáa rẹ̀. A ó sì má a pè é ní: Ìyanu Olùdámọ̀ràn, Ọlọ́run Alágbára Baba ayérayé, Ọmọ ọba aládé Àlàáfíà.

7Ní ti ìgbòòrò Ìjọba rẹ̀ àti àlàáfíà rẹ̀ ni kì yóò ní ìpẹ̀kun. Yóò jọba lórí ìtẹ́ Dáfídì àti lórí ẹ̀kún un rẹ̀ gbogbo, nípa ìfìdímúlẹ̀ àti ìgbéró rẹ̀, pẹ̀lú òtítọ́ àti òdodo láti ìgbà náà lọ àti títí láéláé. Ìtara OLÚWA àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyi ṣẹ.

8OLÚWA ti dojú iṣẹ́ kan kọ Jákọ́bù; Yóò sì wá sórí Ísírẹ́lì.

9Gbogbo ènìyàn ni yóò sì mọ̀ ọ́n— Éfáímù àti gbogbo olùgbé Ṣamáríà— tí ó sọ pẹ̀lú ìgbéraga àti gààrù àyà pé.

10Àwọn bíríkì ti wó lulẹ̀ ṣùgbọ́n a ó tún un kọ́ pẹ̀lú òkúta dídán, a ti gé àwọn igi ọ̀pọ̀tọ́ lulẹ̀ ṣùgbọ́n igi kédárì ní a ó fí dípò wọn.

11Ṣùgbọ́n OLÚWA fún àwọn ọ̀ta Réṣínì ní agbára láti dojúkọ wọ́n ó sì ti rú àwọn ọ̀ta wọn ṣókè.

12Àwọn Árámínì láti ìlà-oòrùn àti Fílístínì láti ìwọ̀ oòrùn

12wọ́n si fi gbogbo ẹnu jẹ́ Ìsirẹli run Ní gbogbo èyí ìbínú un rẹ̀ kò yí kúrò Ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ nà jáde ṣíbẹ̀.

13Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tí ì yípadà sí ẹni náà tí ó lù wọ́n bẹ́ẹ̀ ní wọ́n kò wá OLÚWA àwọn ọmọ-ogun.

14Nítorí náà ni OLÚWA yóò ṣe ké àti orí àti ìrù kúrò ní Ísírẹ́lì, àti Imọ̀-ọ̀pẹ àti koríko-odò ní ọjọ́ kanṣoṣo,

15Àwọn alàgbà, àti àwọn gbajúmọ̀ ni orí, àwọn wòlíì tí ń kọ́ni ní irọ́ ni ìrù.

16Àwọn tí ó ń tọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí sì wọ́n lọ́nà Àwọn tí a sì tọ́ ni a ń sin sí ìparun.

17Nítorí náà, OLÚWA kì yóò dunnú sí àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tàbí kí ó káàánú àwọn aláìní baba àti opó, nítorí pé gbogbo wọn jẹ́ ìkà àti aláìmọ́ Ọlọ́run, ibi ni ó ti ẹnu wọn jáde.

17Ṣíbẹ̀, fún gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò ọwọ́ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.

18Nítòótọ́ ìkà ń jóni bí iná, ó ń jó àtẹ̀wọ̀n, àtẹ̀gùn run, ó sì ń dáná sun ìgbẹ́ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ń yí lọ sókè ní ọ̀wọ̀n èéfín.

19Nípaṣẹ̀ ìbínú OLÚWA àwọn ọmọ-ogun ilẹ̀ náà yóò di gbígbẹ àwọn ènìyàn yóò sì di ohun ìdáná, ẹnìkan kì yóò sì dá arákùnrin rẹ̀ sí.

20Ní apá ọ̀tún wọn yóò jẹrun, síbẹ̀ ebi yóò sì máa pa wọ́n, ní apá òsì, wọn yóò jẹ ṣùgbọ́n, kò ní tẹ́wọn lọ́rùn. Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò sì máa jẹ ẹran-ara ọmọ rẹ̀.

21Mánásè yóò máa jẹ Éfáímù, nígbà tí Éfáímù yóò jẹ Mánásè wọn yóò parapọ̀ dojúkọ Júdà.

21Ṣíbẹ̀síbẹ̀, ìbínú un rẹ̀ kò yí kúrò Ọwọ́ọ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.

e>