Ìwé Wòlíì Ámósì 5:1-27 BYB2014 - Bible AI

1Gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ìwọ ilé Ísírẹ́lì, ìpohùnréré ẹkún tí mo ṣe nípa rẹ:

2“Wúndíá Ísírẹ́lì ṣubú láì kò sì le padà dìde ó di ẹni ìkọ̀tì ní ilẹ̀ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbé e nàró.”

3Èyí ni ohun tí OLÚWA ọ̀gá ògo wí: “Ìlú tí ẹgbẹ̀rún alágbára ti jáde, yóò dín ku ọgọ́run ní Ísírẹ́lì. Ìlú tí ọgọ́run alàgbà ti jáde yóò ṣẹ́ku ẹni mẹ́wàá.”

4Èyí ni ohun tí OLÚWA sọ fún ilé Ísírẹ́lì: “Wá mi kí o sì yè;

5Ẹ má ṣe wá Bẹ́tẹ́lì, Ẹ má ṣe lọ sí Gílígálì Ẹ má ṣe rìnrìn àjò lọ sí Bíáṣébà. Nítorí dájúdájú a ó kó Gílígálì ní ìgbèkùn A ó sì sọ Bẹ́tẹ́lì di asán.”

6Ẹ wá OLÚWA, ẹ̀yin yóò sì yè, Kí ó má ba à gbilẹ̀ bí iná ní Jósẹ́fù A sì jó o run Bẹ́tẹ́lì kò sì ní rí ẹni tí yóò bomi pa á.

6

7Ẹ̀yin tí ẹ̀ sọ òdodo di ìkorò Tí ẹ sì gbé olódodo ṣánlẹ̀

8Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Píláédì àti Óríónì Ẹni tí ó sọ òru dúdú di òwúrọ̀ Tí ó sọ ọjọ́ dúdú di ìmọ́lẹ Ẹni tí ó wọ́ omi òkun jọpọ̀ Tí ó sì rọ̀ wọ́n sí orí ilẹ̀ OLÚWA ni orúkọ rẹ̀,

9Ó fọ́n ìparun sí ìlú olódi Tí ó sì sọ àwọn ibùgbé àwọn ọmọ aládé di ahoro

10Ìwọ kórìíra ẹni tí ń ṣòdì ní ẹnu ibodè ó sì ń pẹ̀gàn ẹni tí ń sọ òtítọ́

10

11Ìwọ ń tẹ talákà mọ́lẹ̀ o ń fi ipá gba ọkà lọ́wọ́ wọn Nítorí náà, ìwọ ti fi òkúta tí a gbẹ́ kọ́lé ṣùgbọ́n ẹ kò sì ní gbé inú wọn Nítòótọ́ ìwọ ti gbin ọgbà àjàrà tí ó lẹ́wà. Ìwọ kò ní mu wáìnì inú wọn

12Nítorí mo mọ iye àìṣedédé rẹ mo sì mọ bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tí tóbi tó.

12Ìwọ ni olódodo lára, ìwọ sì ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ o sì ń fi òtítọ́ du talákà ní ilé ẹjọ́

13Àwọn ọlọgbọ́n máa ń dákẹ́ jẹ́ẹ́ ní àkókò wọ̀nyí Nítorí búburú ni gbogbo ọjọ́.

13

14Wá rere, má ṣe wá búburú kí ìwọ ba à le yè Nígbà náà ni OLÚWA alágbára yóò wà pẹ̀lú ù rẹ. Òun yóò sì wà pẹ̀lú ù rẹ bí ìwọ ṣe wí

15Kòrìírà búburú kí o sì fẹ́ rere Dúró ní orí òtítọ́ ní ilé ẹjọ́ Bóyá OLÚWA Ọlọ́run alágbára yóò síjú àánú wo ọmọ Jósẹ́fù tó ṣẹ́kù

16Nítorí èyí ni ohun tí OLÚWA, Ọlọ́run alágbára wí: “Ẹkún yóò wà ní àwọn òpópónà igbe ìnira yóò sì wà ní àwọn gbàgede ìlú A ó kó àwọn àgbẹ̀ jọ láti sunkún Àti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ láti pohùnréré ẹkún

17Ìpohùnréré ẹkún yóò wà ní gbogbo ọgbà àjàrà Nítorí èmi yóò la àárin yín kọjá,” ni OLÚWA wí.

18Ègbé ni fún ìwọ tí ó pẹ́ nítorí ọjọ́ OLÚWA kí ni ìwọ fi pẹ́ fún ọjọ́ OLÚWA? Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn ní ojú ọjọ́

19Yóò dàbí ọkùnrin tí ó sá láti ẹnu àmọ̀tẹ́kùn. Tí ó padà wá bọ́ sí ẹnu ẹkùn yóò dàbí ẹni tí ó wọ ilé rẹ̀ lọ tí ó simi lé ògiri ilé rẹ̀ tí ejò sì bù ú ṣán.

19

20Ǹjẹ́ ọjọ́ OLÚWA kò ha ní ṣókùnkùn dípò kí ó ní ìmọ́lẹ̀? Tí ó sì ṣókùnkùn dúdú láìsí ìmọ́lẹ̀ kankan níbẹ̀

20

21“Mo kórìíra, mo kẹ́gàn àwọn àṣè ẹ̀sìn in yín Èmi kò sì ní inú dídùn sí àpèjọ yín

22Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú ọrẹ sísun àti ọrẹ ọkà wá Èmi kò ní tẹ́wọ́n gbà wọ́n Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú àṣàyàn ọrẹ àlàáfíà wá. Èmi kò ní náání wọn.

23Ẹ gbé ariwo orin yín sẹ́yìn Èmi kò ní fetísí ohun èlò orin yín.

24Jẹ́ kí òtítọ́ ṣàn bí odò àti òdodo bí ìsun tí kò lé è gbẹ

24

25ⓐ “Àbí ẹ̀yin mú ẹbọ àti ọrẹ tọ̀ mí wá ní ogójì ọdún ní ihà ìwọ ilé Ísírẹ́lì?

26Ẹ̀yin ń gbé ibi ìrúbọ àwọn ọba yín ibùgbé àwọn òrìṣà yín àní, ti àwọn òrìṣà yín tí ó níyì jùlọ, èyí tí ẹ̀yin fi ọwọ́ ara yín ṣe.

27Nítorí náà èmi yóò rán an yín lọ sí ìgbèkùn ní ìkọjá Dámásíkù,” ni OLÚWA wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ọlọ́run alágbára.

>