Ìwé Wòlíì Jeremáyà 39:1-18 BYB2014 - Bible AI

1Bí wọ́n ṣe kó Jérúsálẹ́mù nìyìí: Ní ọdún kẹsàn-án Sedekáyà Ọba Júdà, nínú oṣù kẹwàá. Nebukadinésárì Ọba gbógun ti Jérúsálẹ́mù pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀, wọ́n sì gẹ̀gùn tì í.

2Ní ọjọ́ kẹsàn-án, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Nebukadinésárì wọ́n ya wọ odi ìlú.

3Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè Ọba Bábílónì wá, wọ́n sì jókòó ní àárin ẹnubodè Nágálì Sárésérì.

4Nígbà tí Sedekáyà Ọba Júdà àti àwọn ọmọ ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà Ọba lọ láàrin ẹnubodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.

5Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ ogun Bábílónì lé wọn, wọ́n bá Sedekáyà láàrin ihà Jẹ́ríkò. Wọ́n mú un ní ìgbékùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadinésárì Ọba Bábílónì àti Rábílà ní ilẹ̀ Hámátì, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.

6Níbẹ̀ ní Rábílà, ni Ọba Bábílónì ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekáyà lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Júdà.

7Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekáyà, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Bábílónì.

8Àwọn Bábílónì dáná sun ààfin Ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jérúsálẹ́mù.

9Nebukadinésárì olórí àwọn ọmọ ogun mú lọ sí ìgbékùn Bábílónì pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.

10Ṣùgbọ́n Nebukadinésárì olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Júdà, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.

11Nísinsìnyìí, Nebukadinésárì Ọba àwọn Bábílónì pàṣẹ lórí Jeremáyà, láti ọ̀dọ̀ Nebusárádánì olórí ogun wá wí pé:

12“Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojú tó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”

13Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusárádánì olùdarí ọmọ ogun, Nebusasibánì, olóyè àgbà, Nágálì Sárésà, olóyè àgbà àti gbogbo àwọn olóyè ọba,

14ránṣẹ́ láti mú Jeremáyà kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Jedalíyà ọmọ Álúkámù ọmọ Sápámù láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.

15Nígbà tí Jeremáyà wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ OLÚWA tọ̀ ọ́ wá wí pé:

16“Lọ sọ fún Ebedimélékì ará Kúṣì, ‘Èyí ni ohun tí OLÚWA àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Ísírẹ́lì wí: Èmi ṣetan láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.

17Ṣùgbọ́n Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni OLÚWA wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.

18Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbàgbọ́ nínú mi, ni OLÚWA wí.’ ”

icle>