Ìwé Wòlíì Jeremáyà 8:1-22 BYB2014 - Bible AI

1“ ‘Ní ìgbà náà ni OLÚWA wí pé, wọn yóò mú egungun àwọn ọba Júdà àti egungun àwọn ijoye, egungun àwọn àlùfáà àti egungun àwọn wòlíì àti egungun àwọn olùgbé Jérúsálẹ́mù kúrò nínú ibojì.

2A ó yọ wọ́n síta fún oòrùn àti òṣùpá àti gbogbo àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run tí wọ́n ti fẹ́ràn tí wọ́n sì ti sìn, àti àwọn tí wọ́n ti tọ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti wá tí wọ́n sì ti foríbalẹ̀ fún. Kì yóò ṣà wọ́n jọ tàbí sìn wọ́n, wọn yóò dà bí ìdọ̀tí tó wà lórí ilẹ̀.

3Níbikíbi tí mo bá lé wọn lọ, gbogbo àwọn ìyókù wọn yóò fẹ́ ikú ju ìyè lọ ni OLÚWA Àwọn ọmọ ogun wí.’

4“Wí fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí OLÚWA wí: “ ‘Bí ènìyàn bá ṣubú lulẹ̀ wọn kì í padà dìde bí? Nígbà tí ènìyàn bá yà kúrò ní ọ̀nà rẹ, kì í yí padà bí?

5È é ṣe nígbà náà àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi yà kúrò lọ́nà rẹ̀? Kílódé tí Jérúsálẹ́mù fi yà kúrò ní gbogbo ìgbà? Wọ́n rọ̀ mọ́ ẹ̀tàn, wọ́n kọ̀ láti yípadà.

6Mo ti fetí sílẹ̀ dáradára, wọn kò sọ ohun tí ó tọ́. Kò sí ẹnìkan tó ronúpìwàdà nínú ìwà búburú rẹ̀, kí ó wí pé, “Kí ni mo ṣe?” Olúkúlùkù ń tọ ọ̀nà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹṣin tó ń lọ sójú ogun.

7Kódà, ẹyẹ àkọ̀ ojú ọ̀run mọ ìgbà tirẹ̀, àdàbà, alápáǹdẹ̀dẹ̀ àti lékèélékèé mọ àkókò ìsípòpadà wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kò mọ ohun tí Ọlọ́run wọn fẹ́.

7

8“ ‘Báwo ni ẹ̀yin ṣe lè wí pé, “Àwa gbọ́n, nítorí a ní òfin OLÚWA,” nígbà tí ó jẹ́ pé kálámù èké àwọn akọ̀wé ti àwọn sọ ọ́ di ẹ̀tàn

9Ojú yóò ti àwọn ọlọ́gbọ́n, a ó dà wọ́n láàmú, wọn yóò sì kó sí ìgbèkùn. Nítorí wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ OLÚWA. Irú ọgbọ́n wo ló kù tí wọ́n ní?

10Nítorí náà, èmi yóò fi ìyàwó wọn fún àwọn ọkùnrin mìíràn àti ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹlòmíràn láti èyí tó kéré jù dé èyí tó dàgbà jù, gbogbo wọn ni èrè àjẹjù ń já lẹ́nu; àwọn wòlíì àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ń hùwà ẹ̀tàn.

11Wọ́n tọ́jú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí èyí tí kò jinlẹ̀. “Àlàáfíà, àlàáfíà,” ni wọ́n ń wí, nígbà tí kò sí àlàáfíà.

12Ǹjẹ́ wọ́n tijú fún ìṣe ìríra wọn? Bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn kò ní ìtìjú rárá; wọn kò tilẹ̀ mọ bí wọ́n ti ṣe ń mí oru-ìtìjú. Nítorí náà wọn yóò ṣubú pẹ̀lú àwọn tó ti ṣubú, a ó sì fà wọ́n lulẹ̀ nígbà tí a bá ń fi ìyà jẹ wọ́n, ni OLÚWA wí.

12

13“ ‘Èmi yóò mú ìkórè wọn kúrò ni OLÚWA wí. Kì yóò sí èṣo lórí igi àjàrà, kì yóò sí ọ̀pọ̀tọ́ lórí igi, ewé wọn yóò sì rẹ̀ sílẹ̀. Ohun tí mo ti fi fún wọn ni à ó gbà kúrò.’ ”

13

14“È é ṣe tí a fi jòkó ní ibí yìí? A kó ara wa jọ! Jẹ́ kí a sá lọ sí ìlú olódi kí o sì ṣègbé síbẹ̀. Nítorí tí OLÚWA Ọlọ́run wa ti pinnu pé a ó ṣègbé. Yóò sì fún wa ní omi onímájèlé láti mu, nítorí àwa ti sẹ̀ sí i.

15Àwa ń retí àlàáfíà, kò sí ire kan tí ó wá ní ìgbà ìmúláradá bí kò ṣe ìpayà nìkan.

16Ìró ìfọnmú ẹsin àwọn ọlọ̀tẹ̀ là ń gbọ́ láti Dánì yíyan àwọn akọ ẹsin mú gbogbo ilẹ̀ wárìrì. Wọ́n wá láti pa ilẹ̀ náà run, gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, ìlú náà àti gbogbo olùgbé ibẹ̀.”

16

17“Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró sí àárin yín, paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa oró wọn, yóò sì bù yín jẹ,” ni OLÚWA wí.

17

18Olùtùnú mi, nígbà tí ìbànújẹ́ ọkàn mi rẹ̀wẹ̀sì nínú mi.

19Fetí sí igbe àwọn ènìyàn mi láti ilẹ̀ tó jìn: “OLÚWA kò ha sí ní Síóní bí? Ọba rẹ̀ kò sí níbẹ̀ mọ́ ni?”

19“È é ṣe tí wọ́n fi mú mi bínú pẹ̀lú ère wọn, pẹ̀lú àwọn òrìṣà àjòjì tí wọn kò ní láárí?”

20“Ìkóórè ti ré kọ́ja, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti parí ṣíbẹ̀, a kò gbà wá là.”

20

21Níwọ̀n ìgbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run, èmi náà run pẹ̀lú, mo sọ̀fọ, ìrora sì mú mi káká.

22Kò sí òjé olóòrùn dídùn ní Gílíádì bí? Ṣé kò sí àwọn oníṣègùn níbẹ̀? Kí ló dé tí kò fi sí ìwòsàn fún ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi?

cle>